< Jeremiah 47 >

1 Yahweh gave to the prophet Jeremiah a message about the people of Philistia. [The message was given to me] before Gaza [city in Philistia] was captured by [the army of] Egypt.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tó tọ wòlíì Jeremiah wá nípa àwọn Filistini, kí ó tó di pé Farao dojúkọ Gasa.
2 This is what Yahweh said: “[An army] [MET] will be coming from the northeast that will cover the land like a flood. They will destroy the land and everything in it; [they will destroy] people and cities. People will scream; everyone in the land will wail.
Báyìí ni Olúwa wí: “Wo bí omi ti ń ru sókè ní àríwá, wọn ó di odò tí ń bo bèbè mọ́lẹ̀. Wọn kò ní borí ilẹ̀ àti ohun gbogbo tó wà lórí rẹ̀, ìlú àti àwọn tó ń gbé nínú wọn. Àwọn ènìyàn yóò kígbe, gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà yóò hu
3 [They will hear] the sound of the hooves of the [enemy] horses, and [they will hear] the rumble/noise of the wheels [of their enemies’] chariots. Men [will run away; ] they will not stop to help their children; they will be completely weak and helpless [MTY].
nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ìró títẹ̀lé pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin alágbára nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ọ̀tá ńlá àti iye kẹ̀kẹ́ wọn. Àwọn baba kò ní lè ran àwọn ọmọ lọ́wọ́; ọwọ́ wọn yóò kákò.
4 It will be the time for all the people of Philistia to be destroyed, and the time to prevent the remaining soldiers from helping [the people of] Tyre and Sidon [cities]. [I, ] Yahweh, will get rid of the people of Philistia, those whose ancestors [long ago] came from Crete [island].
Nítorí tí ọjọ́ náà ti pé láti pa àwọn Filistini run, kí a sì mú àwọn tí ó là tí ó lè ran Tire àti Sidoni lọ́wọ́ kúrò. Olúwa ti ṣetán láti pa Filistini run, àwọn tí ó kù ní agbègbè Kafitori.
5 [The people of] Gaza will be humiliated; they will shave off all the hair on their heads [to indicate that they are ashamed]. The [people of] [city] will all be silent [because they will be mourning]. [All you people who live] along the coast [of the Mediterranean Sea] who are still alive, how long [RHQ] will you gash yourselves [because you are mourning]?”
Gasa yóò fá irun orí rẹ̀ nínú ọ̀fọ̀. A ó pa Aṣkeloni lẹ́nu mọ́; ìyókù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò ti sá ara rẹ lọ́gbẹ́ pẹ́ tó?
6 [The people of Philistia say, ] “Yahweh, when [RHQ] will you [tell our enemies to stop killing us with] [PRS] their swords? Tell them to [PRS] put them back into their sheaths and keep them there!”
“Ẹ̀yin kígbe, ‘Yé è, idà Olúwa, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò sinmi? Padà sínú àkọ̀ rẹ; sinmi kí o sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.’
7 But it would not be right [RHQ] for their swords to stay there, because Yahweh has commanded their enemies [to do something more]; Yahweh intends to tell them to attack [all the people living in] Ashkelon and [in other cities] along the coast.
Ṣùgbọ́n báwo ni yóò ṣe sinmi, nígbà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un, nígbà tí ó ti pa á láṣẹ láti dojúkọ Aṣkeloni àti agbègbè rẹ̀.”

< Jeremiah 47 >