< Jeremiah 20 >
1 Pashhur, the son of Immer, was a priest who supervised the temple guards. He heard those things that I had prophesied.
Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
2 [So he arrested me]. Then he [commanded guards to] whip me and fasten my feet in (stocks/a wooden frame) at the Benjamin Gate of Yahweh’s temple.
Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
3 The next day, when Pashhur released me, I said to him, “Pashhur, Yahweh is giving you a new name. From now on, your name will be ‘Surrounded by Terror’,
Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
4 because Yahweh says this [to you]: ‘I will cause you and your friends to be terrified. You will watch them being killed by your enemies’ swords. I will enable the [army of the] king of Babylon to capture the people of Judah. Those soldiers will take some of the people to Babylon, and they will kill others with their swords.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
5 And I will enable their soldiers to take away [other things in] Jerusalem. They will take to Babylon all the very valuable things that belonged to your kings.
Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
6 And [as for] you, Pashhur, they will take you and all your family to Babylon. You and your family and all your friends who have prophesied things that are lies will die there and be buried there.’”
Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
7 [One day I said this to Yahweh]: “Yahweh, [when you chose me to be a prophet, ] deceived me, and I allowed you to deceive me. You insisted that I [become a prophet] and you are stronger than I am. And now everyone [HYP] ridicules me. They make fun of me all the day.
Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
8 When I tell [people your messages], I shout saying, ‘[Yahweh is going to cause you to experience] violence and destruction!’ So because I tell them those messages from you, they insult me and scoff at me all day long.
Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
9 But if I would say, ‘I will never mention Yahweh or say anything about him, [MTY]’ [it would be as though] your message would burn in my inner being like [SIM] a fire; it would be like a fire in my bones. Sometimes I try to remain silent and not proclaim your messages, but I am not able to do that.
Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
10 I hear many people whispering [about me], saying ‘[He is the man who proclaims that there will be things that cause us to] be terrified everywhere. We must tell [the authorities what he is saying]! We must denounce him!’ [Even] my best friends are waiting for me to say something that is wrong. [They are saying], ‘Perhaps we can cause him to say something wrong, and if he does, we will be able to discredit him.’
Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
11 But [you], Yahweh, are helping me like [SIM] a strong warrior, so [it is as though] you will cause those who persecute me to stumble, and they will not defeat me. They will be completely disgraced because of being unable to defeat me; and other people will never forget that they were disgraced.
Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
12 Commander of the armies of angels, you examine [all] those who are righteous; you know [all that is in] their inner beings and what they think. Allow me to see you getting revenge on those [who want to harm me], because I trust that you will do for me what is right.”
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
13 Sing to Yahweh! Praise Yahweh! He rescues [poor and] needy people, from those [SYN] who are wicked.
Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
14 But I hope/desire that the day that I was born will be cursed. I do not want [anyone to] celebrate that day.
Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
15 And [as for] that man who brought to my father the news, and caused him to be very happy, by saying “[You wife] has given birth to a son for you”, I hope/desire that he [also] will be cursed.
Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
16 Allow him to be destroyed like the cities that Yahweh destroyed [long ago], without acting mercifully [toward them]. Cause that man to hear the people wailing in the morning, and [to hear the enemy soldiers shout their] battle cries at noon.
Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
17 [I want that to happen to him] because he did not kill me before I was born. I wish that I had died in my mother’s womb, and that my mother’s body would have been [like] [MET] my grave.
Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
18 I have continually experienced much trouble and sorrow, and I am disgraced now when I am about to die; why was it necessary [RHQ] for me to me born?
Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?