< James 2 >
1 My fellow believers, [because] you trust our Lord Jesus Christ, the one who is glorious/wonderful, stop honoring some people more than others.
Ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí onígbàgbọ́ nínú ògo Olúwa wá Jesu Kristi, ẹ máa ṣe ojúsàájú ẹnikẹ́ni.
2 [For example], suppose that a person who wears gold rings and fine clothes enters your meeting place. Then suppose that a poor person who wears shabby/ragged clothes also comes in.
Nítorí bí ọkùnrin kan bá wá sí ìpéjọpọ̀ yín, pẹ̀lú òrùka wúrà àti aṣọ dáradára, tí tálákà kan sì wá pẹ̀lú nínú aṣọ èérí;
3 And [suppose] that you (show special attention to/treat better) the one who is dressed in fine clothes by saying, “Sit here in this good seat!” and you say to the poor one, “Stand there or sit on the floor [MTY]!”
tí ẹ̀yin sì bu ọlá fún ẹni tí ó wọ aṣọ dáradára tí ẹ sì wí pé, “Ìwọ jókòó níhìn-ín yìí ní ibi dáradára,” tí ẹ sì wí fún tálákà náà pé, “Ìwọ dúró níbẹ̀” tàbí “jókòó níhìn-ín lábẹ́ àpótí ìtìsẹ̀ mi,”
4 Then you have obviously [RHQ] caused divisions in the congregation (OR, you are clearly treating one better than the others, and you are using evil [motives/reasons] to ([evaluate people/decide whether people are important or not])).
ẹyin kò ha ń dá ara yín sí méjì nínú ara yín, ẹ̀yin kò sì di onídàájọ́ tí ó ní èrò búburú bí?
5 Listen [to me], my fellow believers whom I love: God has chosen [RHQ] poor people whom [unbelievers consider to] possess nothing of value, [so that he might bless them] greatly [because] they trust [in him], and in order that they will enter the place where [he] will rule [MET] [forever]. That is what he has promised to those who love him.
Ẹ fi etí sílẹ̀, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́: Ọlọ́run kò ha ti yan àwọn tálákà ayé yìí láti jẹ́ ọlọ́rọ̀ nínú ìgbàgbọ́, àti ajogún ìjọba náà, tí ó ti ṣe ìlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ?
6 But you dishonor the poor people. Think about it! (It is rich people, [not poor people], who are causing you to suffer!/Isn’t it rich people, [not poor people], who are oppressing you?) [RHQ] (It is [the rich people] who forcibly take you to court [to accuse you in front of judges]!/Is it not [the rich people] who forcibly take you to court [to accuse you in front of judges]?) [RHQ]
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti bu tálákà kù. Àwọn ọlọ́rọ̀ kò ha ń pọ́n yin lójú bí; wọn kò ha sì ń wọ́ yín lọ sílé ẹjọ́?
7 (And they are the ones who say evil things about Jesus Christ, the one who is worthy [of praise], to whom you belong!/Are they not the ones who say evil things about Jesus Christ, the one who is worthy [of praise], to whom you belong?) [RHQ]
Wọn kò ha ń sọ ọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ rere nì tí a fi ń pè yín bí?
8 In the Scriptures [God has commanded] each of you to love other people like you love yourself. That commandment was [also given] by [Jesus our] King [MTY]. If you [are loving others], you are doing what is right.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń mú olú òfin nì ṣẹ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́, èyí tí ó wí pé, “Ìwọ fẹ́ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ,” ẹ̀yin ń ṣe dáradára.
9 But if you honor some people more than others, you are (doing wrong/sinning). And because you [do not do what God commanded us to do], he condemns you [PRS] because you disobey his laws.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń ṣe ojúsàájú ènìyàn, ẹ̀yin ń dẹ́ṣẹ̀, a sì ń dá yín lẹ́bi nípa òfin bí arúfin.
10 Do not forget that those who disobey only one of God’s laws, even if they obey all [his other] laws, [God considers them] to be [as guilty as anyone who has disobeyed] all [of] God’s [laws].
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa gbogbo òfin mọ́, tí ó sì rú ọ̀kan, ó jẹ̀bi rírú gbogbo rẹ̀.
11 For example, [God] said, “Do not commit adultery,” but he also said, “Do not murder anyone.” [So] if you [(sg)] do not commit adultery but you [(sg)] murder someone, you [(sg)] have become a person who disobeys [God’s] laws.
Nítorí ẹni tí ó wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” òun ni ó sì wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.” Ǹjẹ́ bí ìwọ kò ṣe panṣágà, ṣùgbọ́n tí ìwọ pànìyàn, ìwọ jásí arúfin.
12 Continually speak and act [toward others] as people should who will be judged {whom [God] will judge} by the law that frees us [from being punished] {[God punishing us]} [for our sins].
Ẹ máa sọ̀rọ̀, ẹ sì máa hùwà, bí àwọn tí a ó fi òfin òmìnira dá lẹ́jọ́.
13 [Speak and act like that], because when [God] judges us, he will not act mercifully toward those who do not act mercifully toward others. But when we [are] merciful [to others, we can rejoice], because [our being] merciful [shows] that [we are acting like people whom God] has mercifully saved from being judged (OR, [we can rejoice] because [God] will judge us mercifully).
Nítorí ẹni tí kò ṣàánú, ni a ó ṣe ìdájọ́ fún láìsí àánú; àánú ń ṣògo lórí ìdájọ́.
14 My fellow believers, [there are some people who say], “I believe [in the Lord Jesus Christ],” but they do not do good things [for other people]. (Their saying that will certainly not do them any good!/What good will their saying that do for them?) [RHQ] [God] will certainly not save [people like that who say that they believe, but do not do good things]! [RHQ]
Èrè kí ni ó jẹ́, ará mi, bí ẹni kan wí pé òun ní ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n tí kò ní àwọn iṣẹ́ láti fihan? Ìgbàgbọ́ náà lè gbà á là bí?
15 [To illustrate], suppose that fellow believers, either men or women, don’t have enough clothing or food for each day.
Bí arákùnrin tàbí arábìnrin kan bá wà ní àìní aṣọ, tí ó sì ṣe àìní oúnjẹ òòjọ́,
16 And suppose that one of you says to them, “May [God] bless you and supply the clothing and food that you need!” but you [(sg)] do not give them the things that they need. (That would be no help [to them]!/What help is that [to them]?) [RHQ]
tí ẹni kan nínú yín sì wí fún pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí ara rẹ kí ó má ṣe tutù, kí ó sì yó,” ṣùgbọ́n ẹ kò fi nǹkan wọ̀n-ọn-nì ti ara ń fẹ́ fún wọn; èrè kí ni ó jẹ́?
17 Similarly, [those who do] not do good things [to help others, what they have said about] their believing [in Christ] is [as useless] [MET] [as] a dead person [is useless]. They do not [really believe in Christ].
Bẹ́ẹ̀ sì ni ìgbàgbọ́, bí kò bá ní iṣẹ́ rere, ó kú nínú ara rẹ̀.
18 But someone may say [to me], “[God saves] some people only [because] they trust [in him], and [he saves] others [because] they do good deeds [to people].” [I would answer that person], “[You(sg) cannot] prove to me that people truly trust [in God if] they do not do good things [for others]. But by doing good things [for others] I will prove to you that I truly trust [in God”]
Ṣùgbọ́n ẹnìkan lè wí pé, “Ìwọ ní ìgbàgbọ́, èmi sì ní iṣẹ́.” Fi ìgbàgbọ́ rẹ hàn mí ní àìsí iṣẹ́, èmi ó sì fi ìgbàgbọ́ mi hàn ọ́ nípa iṣẹ́ rere mi.
19 [Think about it]! You believe that there is only one God, and you are right [to believe that]. But the demons also believe that, but they tremble [with fear because they know that God is going to punish them].
Ìwọ gbàgbọ́ pé Ọlọ́run kan ní ó ń bẹ; ó dára! Àwọn ẹ̀mí èṣù pẹ̀lú gbàgbọ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n sì wárìrì.
20 Also, you foolish person, I will [RHQ] prove to you [(sg)] that [if someone says], “I trust [in God],” but he does not do good things, [what that person says] will not benefit him.
Ṣùgbọ́n, ìwọ aláìmòye ènìyàn, ìwọ ha fẹ́ ní ìdánilójú pé, ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ rere asán ni?
21 (It was certainly [because of] what our [revered] ancestor Abraham did, when he [prepared to] sacrifice his son Isaac, that he was considered [by God] {that [God] considered him} to be a righteous, [obedient] person./Was it not [because of] what our [revered] ancestor Abraham did, when he [prepared to] sacrifice his son Isaac, that he was considered [by God] {that [God] considered him} to be a righteous, [obedient] person?) [RHQ]
Kí ha í ṣe nípa iṣẹ́ ni a dá Abrahamu baba wa láre, nígbà tí ó fi Isaaki ọmọ rẹ̀ rú ẹbọ lórí pẹpẹ?
22 You [(sg)] can realize that he was not only trusting [in God], but he was also doing [what God told him to do], and [you(sg) can realize] that he was able to trust [in God more] completely because of having done [what God told him to do].
Ìwọ rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ bá iṣẹ́ rìn, àti pé nípa iṣẹ́ rere ni a sọ ìgbàgbọ́ di pípé.
23 And [so it happened as it is written in the] Scriptures: “Because Abraham truly trusted in God, he was considered [by God] to be {[God] considered that he was} righteous.” And [God also] said [about Abraham], “He is my friend.”
Ìwé Mímọ́ sì ṣẹ́ tí ó wí pé, “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un,” a sì pè é ní ọ̀rẹ́ Ọlọ́run.
24 [From the example of Abraham], you can realize that it is because people do good things that [God] considers them to be righteous, and not only because they trust [in him].
Ǹjẹ́ ẹ̀yin rí i pé nípa iṣẹ́ rere ni à ń dá ènìyàn láre, kì í ṣe nípa ìgbàgbọ́ nìkan.
25 Similarly, it was certainly [RHQ] [because of] what Rahab did, that [God] considered her to be a righteous, [obedient] person. Rahab was [previously] a prostitute, but she cared for the Israelite men who came [to] ([spy out the land/see what that area was like]) and she [helped them to escape by] sending them home on a different road [from the one that they came on].
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú kí a dá Rahabu panṣágà láre nípa iṣẹ́ bí, nígbà tí ó gba àwọn ayọ́lẹ̀wò, tí ó sì rán wọn jáde gba ọ̀nà mìíràn?
26 Remember that when our spirits [permanently leave our] bodies, [our bodies] are dead [and useless]. Similarly [SIM], [if someone says], “I trust [in God],” but does not do [things to help others, what that person says about trusting in God] is useless.
Nítorí bí ara ní àìsí ẹ̀mí ti jẹ́ òkú, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú ni ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ jẹ́ òkú.