< Isaiah 9 >
1 However, those in Judah who have been distressed/worried will not [continue to] suffer. Previously, Yahweh humbled [the people in] the land [where the tribes of] Zebulun and Naphtali [live]. But in the future he will honor [the people who live in] that Galilee region, along the road between the Jordan [River] and the [Mediterranean] Sea, where [many] foreigners live.
Síbẹ̀síbẹ̀, kò ní sí ìpòrúru kankan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sebuluni sílẹ̀ àti ilẹ̀ Naftali pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Galili ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà Òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jordani.
2 [Some day, it will be as though] [MET] the people who walked in darkness will see a great light. A [great] light will shine on those who live in a land where they have great troubles/distress.
Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá; lórí àwọn tí ń gbé nínú ilẹ̀ òjìji ikú, ní ara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.
3 [Yahweh], you will cause us people in Israel to rejoice; we will become very happy. We will rejoice about what you [have done] like [SIM] people rejoice when they harvest their crops, [or] like soldiers rejoice when they divide up among themselves the things that they have captured in a battle.
Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá; wọ́n sì yọ̀ níwájú rẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkórè, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀ nígbà tí à ń pín ìkógun.
4 You will cause us to no longer be slaves [MET] [of those who captured us]; you will lift the heavy burdens from our shoulders. [It will be as though] you will break the rods of those who oppressed us, like you did when you destroyed [the army of] the Midian people-group.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Midiani, ìwọ ti fọ́ ọ túútúú àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù, ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn, ọ̀gọ aninilára wọn.
5 The boots that the enemy soldiers have worn and their clothing which has stains of blood on them will all be burned up; they will only be fuel for a [big] fire.
Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀, ni yóò wà fún ìjóná, àti ohun èlò iná dídá.
6 Another reason that we will rejoice is that a [special] child will be born for us; [a woman will give birth to] a son, who will be our ruler. And his names will be ‘Wonderful Counselor’, ‘Mighty/Powerful God’, ‘[Our] Everlasting Father’, and ‘Prince/Ruler [who enables us to have] Peace’.
Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fi ọmọkùnrin kan fún wa, ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ̀. A ó sì máa pè é ní Ìyanu Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára, Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.
7 His rule, and the peace that he [brings/causes], will never end. He will rule [MTY] fairly and justly [DOU], like [his ancestor King] David did. This will happen because the Commander of the armies of angels greatly desires that it happen.
Ní ti gbígbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun. Yóò jẹ ọba lórí ìtẹ́ Dafidi àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo, nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀, pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
8 The Lord has warned the people of Israel, the descendants of Jacob; he has said that [he will punish] them.
Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jakọbu; yóò sì wá sórí Israẹli.
9 And all the people in Samaria and [other places in] Israel know that, [but] they are very proud and arrogant [DOU]. They say, “Our city has been destroyed, but we will [take away the broken bricks from the ruins] [and] replace them with carefully cut stones. Our sycamore-fig trees have been cut down [by our enemies], but we will plant cedar trees [in their place].”
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n— Efraimu àti gbogbo olùgbé Samaria— tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga àti gààrù àyà pé.
Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán, a ti gé àwọn igi sikamore lulẹ̀ ṣùgbọ́n igi kedari ní a ó fi dípò wọn.
11 But Yahweh brought the armies of [Assyria], the enemies of King Rezin [of Syria, to fight] against Israel and incited [other] nations [to attack Israel].
Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀tá Resini ní agbára láti dojúkọ wọ́n ó sì ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè.
12 [The army of] Syria [came] from the east, and [the army of] Philistia [came] from the west, and they destroyed Israel [like a wild animal tears another animal apart and] [MET] devours it. But even after that happened, Yahweh was still very angry with them. He was ready to strike them with his fist again.
Àwọn ará Aramu láti ìlà-oòrùn àti Filistini láti ìwọ̀-oòrùn. Wọ́n sì fi gbogbo ẹnu jẹ Israẹli run. Ní gbogbo èyí ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde síbẹ̀.
13 [But even though] Yahweh punished his people [like that], they [still] did not return to him [and worship him]. They [still] did not request the Commander of the armies of angels [to assist them].
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà sí ẹni náà tí ó lù wọ́n bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14 Therefore, in one day Yahweh will get rid of [those who are like] Israel’s head and [those who are like] its tail; the [ones who are like] the top of the palm tree and the [ones who are like] the bottom.
Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrù kúrò ní Israẹli, àti ọ̀wá ọ̀pẹ àti koríko odò ní ọjọ́ kan ṣoṣo,
15 The leaders [DOU] of Israel are the head, and the prophets who tell lies are the tail.
àwọn àgbàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ní orí, àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16 The leaders of the people have misled them; they have caused the people that they are ruling to be confused.
Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣì wọ́n lọ́nà, àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.
17 For that reason, Yahweh is not pleased with the young men [of Israel], and he does not [even] act mercifully toward the widows and orphans, because they are all ungodly and wicked, and they all say things that are foolish. [But] Yahweh still is angry with them; he is ready to strike them with his fist again.
Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó, nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ Ọlọ́run, ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde. Síbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.
18 When people do wicked things, it is like [SIM] a brushfire [that spreads rapidly]. It burns up [not only] briers and thorns; it starts a big fire in the forests from which clouds of smoke will rise.
Nítòótọ́ ìwà búburú ń jóni bí iná, yóò jó ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún run, yóò sì rán nínú pàǹtí igbó, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi gòkè lọ bí ọ̀wọ́n èéfín ti í gòkè.
19 [It is as though] the [whole] land is burned [black] because the Commander of the armies of angels is extremely angry with the Israeli people. They will become like [SIM] fuel for that great fire, and no one will try to rescue even his [own] brother [from that fire].
Nípasẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná, ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.
20 Israeli people will attack their neighbors on the right [to get food from them], but they will still be hungry. They will [kill those who live in houses] on the left and eat their flesh, but their stomachs will still not be full.
Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun, síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n, ní apá òsì, wọn yóò jẹ, ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́ wọn lọ́rùn. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara apá rẹ̀.
21 [People of the tribes of] Manasseh and Ephraim will attack each other, and [then] they will both attack the people of Judah. But even after that happens, Yahweh will still be very angry with them. He will be ready to strike them with his fist again.
Manase yóò máa jẹ Efraimu, nígbà tí Efraimu yóò jẹ Manase wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Juda. Síbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.