< Isaiah 46 >

1 [It is as though] Bel and Nebo, the statues of the gods [of Babylonia], are bowing down as those statues are put on animals and carried away! The statues are heavy burdens and will cause the animals to become tired [SAR]!
Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 [It seems like] both gods are bowing down; not only can they not save themselves, but they themselves are being (exiled/taken to another country)!
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 [Yahweh says], “You descendants of Jacob who were exiled, [I am not like the gods of Babylonia that must be carried]; [instead, it is as though] I have carried you since you first became a nation [MET]. I carried you [even] before you became a nation.
“Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 I will be your God, and I will carry you for many years, until [it is as though] [MET] your nation is an old man with gray hair. I caused [you to become a nation], and I will sustain you and rescue you.
Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 There is certainly [RHQ] no one to whom I can be compared. There is [RHQ] no one who is equal to me [DOU].
“Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 [So it is stupid/ridiculous that] some people pour out gold and silver from their bags and weigh it on a scale. [Then] they hire a man who makes things from gold to make an idol from it. [After he makes an idol], they bow down and worship it!
Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 They lift it up and carry it on their shoulders. They put it in a [special] place, and it stays there. It cannot move! And when someone prays to it, it does not answer. So [obviously] it cannot rescue anyone from his troubles!
Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 [You people of Judah], do not forget this; keep thinking about it, you sinful people!
“Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Think about the things [that I did] long ago. Only I am God; I am God, and there is no one like me.
Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Only I can tell what will happen in the future before it occurs; I tell it long before it happens. I will accomplish everything that I plan to accomplish, and I will do everything that I want to do.
Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 So I will summon [someone to come] from the east [like a swift and powerful] eagle; he will come from a distant country. He will accomplish what I want him to. [He is the one who] will do what I have said that I want him to do, what I have planned.
Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 You stubborn people [of Israel], [you think that] it will be a long time before you are allowed to return to your own country.
Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 But I will rescue you, and it will not be a long time [before that happens]. I will do it soon. I will rescue Jerusalem and show to you Israeli [people] that I am glorious.”
Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.

< Isaiah 46 >