< Isaiah 44 >

1 But now, you people of Israel whom Yahweh has chosen to serve him, listen to me.
“Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
2 Yahweh, the one who created you and helps you, says this: “You dear people of Israel whom I have chosen, you who serve me, do not be afraid.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
3 I will pour water on your dry land and cause streams to flow. And I will pour out my Spirit on your descendants and greatly bless them.
Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
4 They will grow up like [SIM] grass grows along the water, like [SIM] willow/poplar [trees] grow well along a riverbank.
Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
5 Some of them will say, ‘I belong to Yahweh,’ and others will say, ‘We are descendants of Jacob,’ and others will write on their hands, ‘We belong to Yahweh,’ and others will say, ‘We are Israelis.’”
Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
6 Yahweh, the King of Israel, the one who saves us, the Commander of the armies of angels, says this: “I am the one who begins everything and who ends everything; there is no other God.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
7 If there is anyone like me [RHQ], he should proclaim it! He should speak and tell me [now]! He should tell what has happened since I caused my people [of Israel] to become a nation long ago, and he should also tell what things will happen; he should predict what will happen in the future.
Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
8 [My people], do not be afraid. Long ago I told you things that would happen [RHQ]; I predicted them, and you can testify that I did that. There certainly is not [RHQ] any other God. There is no other God who is able to protect you [MET]; I know that there is no other God!”
Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
9 All those who make idols are foolish, and the idols that they (think highly of/greatly respect) are worthless. And the people who worship those idols— [it is as though] they are blind, and they will be ashamed [for having worshiped those idols].
Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
10 Only [foolish people] [RHQ] would make idols in a mold, idols that would never help them at all.
Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
11 Those who make idols and those who worship them will be ashamed. Those who make idols are only human beings, [but they claim that they are making gods]! They should stand in front of God in a court, and [when they hear what he says], they will be terrified, and they will all be disgraced.
Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
12 Metalworkers stand in front of hot coals in order to make idols. They pound them strongly with hammers, and shape them. Because they work very hard, they become hungry and weak; they become very thirsty and feel exhausted.
Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
13 Then a woodcarver takes a big block/piece of wood and he measures it; then he marks it to show where he will cut it. He uses a chisel and other tools to carve it to resemble a human. He causes it to become a very beautiful [idol], and then he puts it in a shrine.
Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
14 [Before he carves an idol from that block of wood], he has cut down a cedar tree, or he has selected a cypress tree or an oak tree and allowed it to grow tall in the forest. Or, he has planted a pine/evergreen tree and the rain has watered it [and caused it to grow tall].
Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
15 [And after he uses part of the tree to make an idol], he uses the other part of the tree to make a fire, either to warm himself or to bake bread. But he uses [part of the same tree] to make for himself an idol to worship! He makes an idol and then he bows down to worship it.
Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
16 He burns part of the wood of the tree to cook his meat and eats the meat and his stomach becomes full, and he burns part of the wood to warm his body, and he says, “I feel warm while I am watching the flames in the fire.”
Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
17 Then he takes the rest of the wood and makes an idol which is his god. He bows down to it and worships it, and prays to it and says, “You are my god, so save me!”
Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
18 Those people are very stupid and ignorant [SAR]. [It is as though] they are blind and cannot see, and their minds are closed and they cannot think well.
Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
19 They do not think about what they are doing, that they are taking a block of wood and burning half of it to warm themselves and using some of the rest to bake bread and roast some meat! [They do not say to themselves], “It is stupid [RHQ] to take the rest of the wood to make a detestable idol! It does not make sense to bow down to a block of wood!”
Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
20 They are very stupid to [worship something that if you burn it, it becomes] ashes! They trust in something that cannot save them; they do not admit, “In my hand I hold something that is not really a god! [RHQ]”
Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
21 [Yahweh says, “You descendants of] [MTY] Jacob, you people of Israel who should be serving me, I created you, and I will not forget you.
“Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
22 I have gotten rid of your sins like [SIM] [the wind blows away] a cloud. [It is as though] your transgressions were a morning mist [SIM] that I have blown away. Return to me because I have rescued you.”
Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
23 [The sun and moon and stars] in the sky should sing, and all the things that are beneath the ground should shout joyfully! All the mountains and forests, and all you trees, should sing loudly, because Yahweh has rescued [the descendants of] [MTY] Jacob; [the people of] Israel will praise/honor him.
Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
24 Yahweh, who saved you and created you, says this: “I am Yahweh, the one who created everything. I am the only one who stretched out the sky. There was [RHQ] no one who (was with/helped) me when I created the earth.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
25 I show that the false prophets are liars, and I show that those who perform rituals to predict the future are fools. Some people who [falsely think that they] are [IRO] wise [say that they] know a lot, but I show that they are foolish.
ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
26 But I always cause to happen what my prophets predict [DOU]. [I tell them to] say to [the people of] [MTY] Jerusalem, ‘[Some day] people will live here again.’ [And I tell them to] say to [the people in other] towns in Judah [that Yahweh says], ‘Your towns will be rebuilt; I will cause the places that are only ruins to be rebuilt.’
ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
27 When I say to the rivers, ‘Dry up!’, they will become dry.
ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
28 When I say about King Cyrus, ‘He will [take care of my people like] [MET] a shepherd [takes care of his sheep], he will do what I want him to do,’ he will say about Jerusalem, ‘We must rebuild it!’, and he will also say, ‘We must rebuild the temple!’”
ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”

< Isaiah 44 >