< Isaiah 40 >

1 Our God says, “Encourage my people! Encourage them!
Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú, ni Ọlọ́run yín wí.
2 Speak kindly to [the people of] Jerusalem; tell them that their suffering is ended, and that I have forgiven them for the sins that they have committed; I [SYN] have fully punished them for their sins.”
Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu kí o sì kéde fún un pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí, pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
3 I hear someone who is shouting, “Prepare in the desert a way for Yahweh to come [to you]; make a smooth road for our God (OR, Prepare yourselves to receive Yahweh when he comes, like people make a straight road for an important official [MET]).
Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù: “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
4 Fill in the valleys; flatten every hill and every mountain. Make the uneven ground smooth, and make the rough places smooth.
Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé sókè, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀; wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ.
5 [If you do that], it will become known that Yahweh is glorious/great, and all people will realize it at the same time. [Those things will surely happen] because it is Yahweh who has said [MTY] it.”
Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀, gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i. Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”
6 Someone said to me, “Shout!” I replied, “What should I shout?” [He replied], “[Shout that] people are like [SIM] grass; their influence fades as quickly as flowers in the field.
Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.” Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?” “Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko, àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
7 Grass withers and flowers dry up when Yahweh causes a hot wind from the desert to blow on them. And people are [MET] like that.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n. Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
8 The grass withers and the flowers dry up, but what our God promises will last forever.”
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”
9 You [people of] Jerusalem, you have good news to tell to people, so, shout it from the top of a high mountain! Shout it loudly, and do not be afraid! Tell the people in the towns of Judah, “Your God is coming here!”
Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni, lọ sí orí òkè gíga. Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu, gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo, gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú u Juda, “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
10 Yahweh your God will be coming with power; he will rule powerfully [MTY]. And when he comes, he will bring with him the people whom he has freed [MET] [from being slaves in Babylonia].
Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára, apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un. Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀, àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
11 He will take care of his people like [SIM] a shepherd takes care of his sheep, and carries the young lambs in his arms. He carries them close to his chest and he gently leads the female sheep that are nursing their young lambs.
Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn: Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀. Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀; ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.
12 [There is no one like Yahweh]! (Who else has measured the water in the oceans in the palm of his hand?/No one else has measured the water in the oceans in the palm of his hand!) [RHQ] (Who else has measured the sky with his fingers?/No one else has measured the sky with his fingers!) [RHQ] (Who else knows how much the earth weighs?/No one else knows how much the earth weighs!) [RHQ] (Who else has weighed the mountains and hills on scales?/No one else has weighed the mountains and hills on scales!) [RHQ]
Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀, tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀ tí ó wọn àwọn ọ̀run? Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀, tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n àti òkè kéékèèké nínú òsùwọ̀n?
13 And (who else can advise Yahweh’s Spirit?/No one else can advise Yahweh’s Spirit!) [RHQ] (Who can teach him or advise/tell him what he should do?/No one can teach him or advise/tell him what he should do!) [RHQ]
Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa, tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 (Has Yahweh consulted anyone else to get advice?/Yahweh has certainly not consulted anyone else to get advice!) [RHQ] (Does he need someone to tell him what is right to do and how to act justly?/He certainly does not need someone to tell him what is right to do and how to act justly!) [RHQ]
Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́? Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?
15 [Yahweh considers that] the nations are [as insignificant as] [MET] one drop from a bucket [full of water]. They are [as insignificant as] dust on scales. He is able to weigh islands [as though they weighed no more than] grains of sand.
Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi nínú garawa; a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n; ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
16 There would be [not] enough wood from all the trees in Lebanon to make a suitable fire for [sacrificing animals to] him, and there are not enough animals in Lebanon to offer as sacrifices to him.
Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná, tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
17 The nations of the world are completely insignificant/unimportant to him; he considers that they are worthless and less than nothing [HYP, DOU].
Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí; gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò tí kò tó ohun tí kò sí.
18 So, to whom can you compare God? What image resembles him?
Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé? Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 Can you compare him to an idol that is made in a mold, and then is covered with [a thin sheet of] gold and decorated with silver chains?
Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á, ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
20 A man who is poor [cannot buy silver or gold for his idol]; [so] he selects a piece of wood that will not rot, and he gives it to a craftsman to carve an idol that will not fall down!
Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá, wá igi tí kò le è rà. Ó wá oníṣọ̀nà tí ó láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.
21 Have you(pl) not heard this? Do you not understand it? Are you unable to hear what God said long ago— [messages that he gave] before he created the earth?
Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀ ìwọ kò tí ì gbọ́? A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá? Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
22 God sits [on his throne] above the earth, and the people [on the earth] below seem to be [as small] as [SIM] grasshoppers. He spreads out the sky like a curtain; it is like [SIM] a tent for him to live in.
Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé, àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata. Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà, ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
23 He causes kings to have no more power, and he causes the rulers to be worth nothing.
Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
24 They start to rule, like small plants start to grow and form roots; but then [he gets rid of them] as though [MET] they withered when he blew on them, like [SIM] chaff that is blown away by the wind.
Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n, kété tí a gbìn wọ́n, kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ, bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.
25 The Holy One asks, “To whom will you compare me? Is anyone equal to me?”
“Ta ni ẹ ó fi mi wé? Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
26 Look up toward the sky: Consider who [RHQ] created all the stars. [Yahweh created them], and at night he causes them to appear; he calls each one by its name. Because he is extremely powerful [DOU], all of the stars are there [LIT] [when he calls out their names].
Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run. Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí? Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan. Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.
27 You people of Israel [DOU], why do you complain that Yahweh does not see the [troubles that you are experiencing]? Why do you say that he does not act fairly toward you?
Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu? Àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli, “Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa; ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
28 Have you never heard and have you never understood that Yahweh is the everlasting God; he is the one who created the earth, [even the] most distant places on the earth. He never becomes weak or weary, and no one can find out how much he understands.
Ìwọ kò tí ì mọ̀? Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé, Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé. Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀, àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
29 He strengthens [DOU] those who feel weak and tired.
Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
30 Even youths become faint and weary, and young men will fall when they are exhausted.
Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
31 But those who trust in Yahweh will become strong again; [it will be as though] they will soar/fly high like [SIM] eagles do. They will run [for a long time] and not become weary; they will walk [long distances] and not faint.
ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun. Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì; wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn, wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.

< Isaiah 40 >