< Isaiah 30 >

1 Yahweh says, “Terrible things will happen to you, my people who rebel against me. You make plans, but what you plan is not what I want. You have made an alliance [with the rulers of Egypt], but you did not ask my Spirit [if that was what you should do]. By doing that, you have increased the number of your sins.
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 You went to Egypt [to ask their rulers for help], without asking for my advice. You have trusted in [the army of] the king of Egypt to protect you; you have [trusted in them] [like] people sit in the shade [to protect themselves from the sun] [MET].
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 [But] the result of your trusting in the king of Egypt is that you will be [disappointed and] disgraced; because of trusting in him, you will be humiliated.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 Officials/ambassadors [from Judah] have gone to Zoan and Hanes [cities in Egypt to make treaties],
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 but all those [who trust in the King of Egypt] will be humiliated, because that nation will not be able to help you; the treaty that you have made [requesting help from them] will be useless; instead, the result will be that you will be humiliated and disgraced [DOU].”
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 [I received from Yahweh] this message about the animals in the southern part of Judah: That area is one where [people experience a lot of] troubles and difficulties, an area where there are male and female lions and various kinds of poisonous snakes. Caravans go through that area taking donkeys and camels loaded with valuable goods. [They are taking them] to Egypt to seek for protection [by the army of Egypt], [but] it will be useless.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 The promises made by [the king of] Egypt are worthless; therefore I call Egypt ‘the sea monster/dragon that does nothing’.
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Yahweh told me to write on a scroll a message, in order that it would be a witness [to the people of Judah] that would endure forever.
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 [It would remind them] that they are deceitful and always rebelling against Yahweh; they refuse to pay attention to what he tells/teaches them.
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 They tell the people who see/receive visions [from Yahweh], “Stop seeing visions!” They tell the prophets, “Do not reveal to us what is right! Tell us pleasant things; do not tell us visions about things that are true!
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Stop doing what you have been doing [DOU]; stop telling us what the Holy One of Israel [says to us]!”
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Therefore, this is what the Holy One of Israel says: “You have rejected my message, and you are relying on those who oppress and deceive others.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 Therefore, the result of your sin [of rejecting me] will be that you will [suddenly experience disasters]; what will happen to you will be like [SIM] a cracked wall that suddenly collapses [DOU].
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 You will be smashed like a clay jar is smashed [when it is dropped], and it shatters completely, with the result that there is not one piece big enough to carry some coals from a stove or to carry a little bit of water from a well.”
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
15 Yahweh, [our] God, the Holy One of Israel, [also] says this: “You will be rescued [from your enemies only] if you repent and trust [in what I will do for you]; you will be strong [only] if you quit worrying and trust in me. But you do not want [to do that].
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 You said, ‘No, we will escape on horses [that the army of Egypt will give us]!’ So, you will [try to] flee. You said, ‘We will [escape from the army of Assyria] by riding on swift horses!’ [But] those who pursue you will [also ride] swiftly.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 [As a result], 1,000 [of you] will flee when [only] one of them pursues you! When only five [of their soldiers] threaten [to kill you], [all of] will flee. [Only a few of] you will be left, like [SIM] a [single] flagpole on top of a mountain with one signal flag on the pole.”
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 [But] wants to be kind to you; he desires to show you that he is merciful. [Do not forget that] Yahweh is a God who acts justly; he is pleased with those who patiently trust in him.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 You people who live in Jerusalem [DOU], [some day] you will not cry any more. Yahweh will be kind to you when you call out to him for help. He will answer/help you as soon as he hears you call.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 Although [now] Yahweh has caused you to [daily] experience [MET] great troubles and suffer much, [he], your teacher, will not hide himself from you. He [SYN] will teach you many things clearly.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 And you will hear him speak to you to guide you. [Right] behind you he will say, “This is the road on which you should walk; walk on this road!”
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 When that happens, you will destroy [all] your idols that are covered with silver or gold. You will throw them away like you throw away a filthy rag, and you will say to them, “We do not need you any more!”
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 [If you do that], Yahweh will bless you by giving you good rain at the time that you plant your crops. You will have good harvests, and plenty of pasture with grass for your cattle to eat.
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 After the wind [blows away the chaff], the oxen and donkeys that [pull the plow to] plow your ground will have good grain to eat.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 At that time, when [your enemies] have been slaughtered and their towers have (collapsed/been destroyed), there will be streams flowing down every hill and mountain [in Judah].
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 The moon will seem to shine as brightly as the sun, and the sun will seem to shine seven times as brightly as previously. That is what it will be like when Yahweh causes [the suffering of] his people [to cease; it will be as though] [MET] he will be putting bandages on their wounds and healing them.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 [It is as though] we see Yahweh coming from far away; he is extremely angry, and there are thick clouds of smoke around him. By what he says [MTY] he shows that he is angry; what he says is like [SIM] a devastating/destructive fire.
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 His breath is like [SIM] a flood that covers [his enemies] up to their necks. He will separate [MET] the nations in order to destroy [some of them]; [it is as though] he will put hooks in their mouths and take them away.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 But [his people] will sing joyfully like they sing during the nights when they celebrate a holy festival. They will be very joyful, like [SIM] [a large group of his people] are joyful when they go up to Zion Hill in Jerusalem, along with men playing flutes [when they are all going there to worship Yahweh]. He is [like] [MET] a huge rock under which [we] Israeli people [are safe].
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 And Yahweh will enable [us] to hear him speaking powerfully/majestically. He will show us that he [SYN] is very powerful. [We] will see him [SYN] smash [his enemies]. Being very angry, he will descend with a big rainstorm and thunder and hail [to punish them].
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 [The soldiers of] Assyria will be terrified when they hear the voice of Yahweh and when he strikes them with his rod.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 And while Yahweh strikes them to punish them, [his people] will [celebrate by] playing tambourines and harps. [It will be as though] Yahweh will lift up his powerful hand/arm and defeat the Assyrian army in battle.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 [The valley of] Topheth [outside Jerusalem] has been prepared for a long time; it is ready for the king [of Assyria]; the (funeral pyre/pile of wood) [for burning his body] is wide and high, and [it will be as though] Yahweh will light the fire with his breath, which will come out like a stream of burning sulfur.
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

< Isaiah 30 >