< Isaiah 22 >

1 [I received] this message [from Yahweh] about Jerusalem, about the valley where [Yahweh showed me] this vision. Why is everyone foolishly running up to their [flat] rooftops?
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran. Kí ni ó ń dààmú yín báyìí, tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
2 Everyone in the city [seems to] be shouting. [There are a lot of] corpses [in the city], [but they] were not killed by [their enemies’] swords. They did not die in battles; [instead, they died from diseases and hunger].
Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò, ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
3 All the leaders of the city fled. [But then] they were captured because they did not have bows [and arrows to defend themselves]. Your [soldiers tried to] flee while the enemy [army] was still far away, but they also were captured.
Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ; a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà. Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀, lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà lọ́nà jíjìn réré.
4 That is why I said, “Allow me to cry alone; do not try to comfort me [about my people being slaughtered].”
Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi: jẹ́ kí n sọkún kíkorò. Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
5 The Commander of the armies of angels has [chosen] a time when there will be a great uproar, [soldiers] marching, and people being terrified in the valley [where I received this] vision. [It will be a time when our city] walls will be battered down and [the people’s] cries [for help] will be heard in the mountains.
Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan tí rúkèrúdò àti rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ ní àfonífojì ìmọ̀, ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀ àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
6 The armies from Elam and Kir [in Media] will attack, driving chariots and carrying shields.
Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin, Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
7 Our beautiful valleys will be filled with [our enemies’] chariots and the men who drive the chariots will stand outside [our city] gates.
Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
8 The walls that protect [the cities in] Judah will fall down. You [people of Jerusalem] will run to get the weapons [that are stored in the building called] “the Hall of the Forest”.
Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò. Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù.
9 You will see that there are many breaks/holes in the walls of Jerusalem. You will store water in the lower pool [in the city].
Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀, ìwọ ti tọ́jú omi sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
10 You will inspect the houses in Jerusalem, and [some of] them you will tear down to use the stones to repair the [city] wall.
Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
11 Between the walls [of the city] you will build a reservoir to [store] water from the old pool. But you will never request help from the one who made the city; you have never depended on Yahweh, who planned this city long ago.
Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì fún omi inú adágún àtijọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀ tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.
12 The Commander of the armies of angels told you to weep and mourn; he told you to shave your heads and to wear rough sackcloth to show that you were sorry for the sins that you had committed.
Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun, pè ọ́ ní ọjọ́ náà láti sọkún kí o sì pohùnréré, kí o tu irun rẹ dànù kí o sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 But instead of doing that, you were happy and celebrating; you slaughtered cattle and sheep, [in order to cook their] meat and eat it and drink wine. You said, “Let’s eat and drink [all that we want to], because [it is possible that] we will die tomorrow!”
Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà; màlúù pípa àti àgùntàn pípa, ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu! Ẹ̀yin wí pé, “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu, nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”
14 [So] the Commander of the armies of angels revealed this to me: “I will never forgive my people for sinning like this!”
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
15 The Commander of the armies of angels said this [to me]: “Go to Shebna, the official who supervises the workers in the palace, and give this message to him:
Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé, fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
16 '[Who do you think you are?] Who gave you the authority to build a beautiful tomb where you will be buried, chiseling it out of the rocky cliff high above this valley?
Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín yìí, tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?
17 You [think that you are] [IRO] a great man, but Yahweh is about to hurl you away. [It will be as though] he will seize you,
“Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí kí ó sì jù ọ́ nù, ìwọ ọkùnrin alágbára.
18 and roll/crumple you into a ball and throw you away into a large distant land. You will die [and be buried] there, and your beautiful chariots will stay there [in the hands of your enemies]. And [because of what happens to you], your master, [the king], will be [very] ashamed/disgraced.
Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà— ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
19 Yahweh will force you to quit working in the palace; you will be demoted from your important position.
Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ, a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.
20 Then I will summon Hilkiah’s son Eliakim, who has served serve me [well], to replace you.
“Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
21 I will allow him to wear your robe, and to fasten your sash around him, and I will give to him the authority that you had. He will be like [MET] a father to the people of Jerusalem and [all the other] towns in Judah.
Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
22 I will give to him authority [MTY] over [what happens in] the palace where King David [lived]; when he decides something [MET], no one will be able to oppose it; when he refuses to do something, no one will be able to force him to do it.
Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
23 I will cause his family to be greatly respected, because I will put him firmly in his position [as supervisor of the workers in the palace], like [SIM] a nail that is firmly hammered into a wall.
Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
24 Others will enable him to have much responsibility, with the result that all the members of his family, even the most insignificant ones, will be honored.'”
Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
25 [But] the Commander of the armies of angels also says, “[Shebna is like] [MET] a peg that is firmly fastened to the wall. But there will be a time when I will [remove him from his position]; he will lose his power/influence, and everything that he promoted [MET] will fail. [That will surely happen] because [I], Yahweh, have said it.”
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

< Isaiah 22 >