< Isaiah 21 >
1 [I received] this message [from Yahweh about Babylonia], [a land that is] near the [Persian] Gulf [but which will soon be] a desert. [An army] will soon come from the desert to invade that land; it is an army that causes its enemies to be terrified, an army that will come like a whirlwind from the south.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun. Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù, akógunjàlú kan wá láti aginjù, láti ilẹ̀ ìpayà.
2 Yahweh showed me a terrifying vision. [In the vision I saw an army] that will betray/deceive people and steal their possessions [after they conquer them]. [Yahweh said], “You armies from Elam and Media, surround [Babylon] and prepare to attack it! I will cause the groaning [and suffering] that Babylon caused to cease!”
Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo ìpayínkeke dópin, ni ó búra.
3 Because of that, my body is full of pain; my pain is like the pain that women who are giving birth experience. When I hear about and see [what God is planning to do], I am shocked.
Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí, ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
4 I cannot think straight/correctly, and I tremble. I was eager for it to be nighttime, but now it is night, and I am horrified.
Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.
5 [In the vision I saw that the leaders of Babylonia] were preparing a great feast. They had spread rugs [for people to sit on]; everyone was eating and drinking. [But] they should get up and prepare their shields, [because they are about to be attacked]!
Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé, ẹ fi òróró kún asà yín!
6 Then Yahweh said to me, “Put a watchman [on the wall of Jerusalem], and tell him to shout/proclaim what he sees.
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
7 Tell him to watch for chariots pulled by pairs of horses, and [men riding] camels and donkeys, [coming from Babylon]. Tell the watchman to watch and listen carefully!”
Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”
8 [So I did that], and one day the watchman called out, “Day after day I have stood on this watchtower, and I have continued to watch during the day and during the night.
Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán, a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
9 Now, I saw a man riding in a chariot pulled by two horses. [I called out to him], and he answered/shouted, ‘Babylon has been destroyed! All the idols in Babylon lie in pieces on the ground!’”
Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀ ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’”
10 My people [in Judah], [the army of Babylon has caused] you to suffer greatly [as though] [MET] you were grain that was threshed and (winnowed/thrown up into the air for the wind to blow away the chaff). [But now] I have told you what the Commander of the armies of angels the God whom we Israelis [worship], told me [about Babylon].
Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.
11 [I received] this message [from Yahweh] about Edom: Someone from Edom has been calling/shouting to me saying, “Watchman, how long will it be before the night is ended? [DOU]”
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi. Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá, “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
12 [I], the watchman, replied, “It will [soon] be morning, but after that, it will [soon] be night again. If you want to inquire [again about what will happen in our country], come back and inquire again.”
Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè; kí o sì tún padà wá.”
13 [I received] this message about Arabia: Give this message to people traveling in caravans from Dedan [town in northwest Arabia], who camp in the scrub there. Tell them to bring water for those who are thirsty.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia. Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
14 And you people who live in Tema [city in northwest Arabia], must bring food for the (refugees/people who are fleeing from their enemies).
gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
15 They are fleeing in order not to be killed by [their enemies’] swords and not to be shot in battles by arrows.
Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ àti kúrò nínú ìgbóná ogun.
16 Yahweh said to me, “Exactly one year from now, all the greatness of the Kedar [area in Arabia] will end.
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo ìlú Kedari yóò wá sí òpin.
17 Only a few of their soldiers who know well how to shoot arrows will remain alive. [That will surely happen] because [I], Yahweh, have said it.”
Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun ìlú Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.