< Isaiah 16 >
1 [The rulers of Moab will say to each other, ] “We must send some [lambs] from Sela [city] as a gift to the ruler of Judah [to persuade him to not allow his army to attack us any more]. We should send them through the desert to the king.
Fi ọ̀dọ́-àgùntàn ṣe ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí aláṣẹ ilẹ̀ náà, láti Sela, kọjá ní aginjù, lọ sí orí òkè ọ̀dọ́mọbìnrin Sioni.
2 The women of Moab will be left alone at the (fords of/places where people can walk across) the Arnon [River]; they will be like [SIM] birds that have been pushed out of their nests.
Gẹ́gẹ́ bí alárìnkiri ẹyẹ tí a tì jáde kúrò nínú ìtẹ́, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn obìnrin Moabu ní àwọn ìwọdò Arnoni.
3 They will cry out, ‘Help us! Tell us what we should do! Protect us completely [MET], we who are running away [from our enemies], and do not (betray us/tell our enemies where we are).
“Fún wa ní ìmọ̀ràn ṣe ìpinnu fún wa. Jẹ́ kí òjìji rẹ dàbí òru, ní ọ̀sán gangan. Fi àwọn ìsáǹsá pamọ́, má ṣe fi àwọn aṣàtìpó han.
4 Allow [those of us] who are fleeing from Moab to stay with you; hide/protect us from [our enemies who want to] destroy us!’ [Some day] there will be no one to oppress us, and our enemies will stop destroying [our land].
Jẹ́ kí àwọn ìsáǹsá Moabu gbé pẹ̀lú rẹ, jẹ́ ààbò fún wọn kúrò lọ́wọ́ ìparun.” Aninilára yóò wá sí òpin, ìparun yóò dáwọ́ dúró; òfinràn yóò pòórá kúrò lórí ilẹ̀.
5 Then [Yahweh] will appoint someone to be king who will be [a descendant of King] David. As he rules [MTY], he will be merciful and truthful. He will always do what is fair/just and quickly do what is righteous.”
Nínú ìfẹ́ a ó fi ìdí ìjọba kan múlẹ̀, ní òdodo ọkùnrin kan yóò jókòó lórí rẹ̀ ẹnìkan láti ilé Dafidi wá. Ẹni yóò ṣe ìdájọ́, yóò sì máa wá ìdájọ́, yóò sì máa yára wá ohun tí í ṣe òdodo.
6 We [people of Judah] have heard about [the people of] Moab; we have heard that they are very proud and conceited [DOU]; they are insolent, but what they proudly say about themselves is not true.
Àwa ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu, ìwọ̀sí ìgbéraga rẹ̀ àti fùlenge fùlenge, gààrù rẹ̀ àti àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n ìfọ́nnu rẹ̀ jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.
7 [Some day all the people in] Moab will weep. They will all mourn, because [there will be no more] raisin cakes in Kir-Hareseth [city].
Nítorí náà ni àwọn ará Moabu hu, wọ́n jùmọ̀ hu lórí Moabu. Sọkún kí o sì banújẹ́ fún àkàrà díndín Kiri-Hareseti.
8 The [crops in] the fields at Heshbon [city] will wither, and the vineyards at Sibmah [town] will wither also. The armies of [other] nations will destroy Moab, which is [like] [MET] a beautiful grapevine whose branches spread [north] to Jazer [town] and [east] to the desert. Its branches spread very far [west], to the west side of the [Dead] Sea.
Gbogbo pápá oko Heṣboni ti gbẹ, bákan náà ni àjàrà Sibma rí. Àwọn aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n tẹ àwọn àyànfẹ́ àjàrà mọ́lẹ̀, èyí tí ó ti fà dé Jaseri ó sì ti tàn dé agbègbè aginjù. Àwọn èhíhù rẹ̀ fọ́n jáde, ó sì lọ títí ó fi dé Òkun.
9 So I will weep for Jazer and for the grapevines of Sibmah. I will shed tears for all of you. I will cry because people will no longer shout joyfully, like they usually do when they gather the fruit that ripens in the (summer/hot season) and the other crops that they harvest.
Nítorí náà mo sọkún, gẹ́gẹ́ bí Jaseri ṣe sọkún, fún àwọn àjàrà Sibma. Ìwọ Heṣboni, ìwọ Eleale, mo bomirin ọ́ pẹ̀lú omi ojú! Igbe ayọ̀ lórí àwọn èso pípọ́n rẹ àti lórí ìkórè èyí tí o ti mọ́wọ́ dúró.
10 People will no longer be glad at harvest time. No one will sing in the vineyards, no one will shout joyfully. No one will tread on grapes [to get grape juice for wine]; there will be nothing to shout about [joyfully].
Ayọ̀ àti ìdùnnú ni a ti mú kúrò nínú ọgbà-igi eléso rẹ; kò sí ẹnìkan tí ó kọrin tàbí kígbe nínú ọgbà àjàrà: ẹnikẹ́ni kò fún ọtí níbi ìfúntí, nítorí mo ti fi òpin sí gbogbo igbe.
11 I cry inwardly for Moab; my groaning is like [SIM] [a sad song played on] a harp. I am sad about Kir-Hareseth.
Ọkàn mi kérora fún Moabu gẹ́gẹ́ bí i dùùrù, àní tọkàntọkàn mi fún ìlú Kiri-Hareseti.
12 [The people of] Moab will go and pray at their sacred shrines, but that will not help them. They will cry out to their gods in their temples, [but] none of them will be able to rescue the people.
Nígbà tí Moabu farahàn ní ibi gíga rẹ̀, ó ṣe ara rẹ̀ ní wàhálà lásán; nígbà tí ó lọ sí ojúbọ rẹ̀ láti gbàdúrà òfo ni ó jásí.
13 Yahweh has already spoken those things about Moab.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa Moabu.
14 But now he says that exactly three years from now, he will destroy all the things that [the people of] Moab have been proud of. Even though they have a huge number of people in Moab now, only a few people will remain alive, and they will be weak/helpless.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí Olúwa wí pé, “Láàrín ọdún mẹ́ta gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ìdè ọgbà rẹ̀ ti máa kà á, ògo Moabu àti àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn rẹ̀ ni a ó kẹ́gàn, àwọn tí ó sálà nínú rẹ̀ yóò kéré níye, wọn yóò sì jẹ́ akúrẹtẹ̀.”