< Isaiah 13 >
1 [I], Isaiah, the son of Amoz, received [from Yahweh] this message about Babylon [city]:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí.
2 Lift up a flag on the bare [top of a] hill, to signal [that an army should come to attack Babylon]. Shout to them and wave your hand [to signal to them] that they should march through the city gates into the palaces of the proud [rulers of Babylon]!
Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu, kígbe sí wọn, pè wọ́n láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
3 [Yahweh says], “I have commanded those soldiers to do that; I have summoned the warriors whom I have chosen to punish [the people of Babylon] because of my being very angry with them, and those soldiers will be very proud [when they do that].”
Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi, mo ti pe àwọn jagunjagun mi láti gbé ìbínú mi jáde àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.
4 Listen to the noise on the mountains, which is the noise of a huge army marching! It is the noise made by people of many people-groups shouting. The Commander of the armies of angels has summoned this army to gather together.
Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè, gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn. Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba, gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ àwọn jagunjagun fún ogun.
5 They come from countries that are far away, from the most remote places [IDM] on the earth. They are [like] [SIM] weapons that Yahweh will use [to punish the people with whom] he is very angry, and to destroy the entire country [of Babylonia].
Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré, láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀, láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.
6 [You people of Babylon] will scream because you will be terrified, because it will be the time that Yahweh [has determined/chosen], the time for the all-powerful [God] to destroy [your city].
Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
7 All of your people will be very afraid [DOU], with the result that they will be unable even to lift their arms.
Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ, ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
8 All of you will be terrified. You will have [PRS] severe pains like [SIM] a woman has when she is giving birth to a baby. You will look at each other helplessly, and it will show on your faces that you feel horror.
Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú, ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú, wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí. Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà ojú wọn á sì gbinájẹ.
9 Listen to this: The day that Yahweh has appointed/chosen is near, the day that he will furiously and fiercely [punish you] because he is very angry [with you]. He will cause your land [of Babylonia] to be desolate/barren, and he will destroy [all] the sinners in it.
Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú àti ìrunú gbígbóná— láti sọ ilẹ̀ náà dahoro, àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
10 [When that happens], none of the stars will shine. When the sun rises, it will be dark, and there will be no light from the moon [at night].
Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn. Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
11 [Yahweh says], “I will punish [everyone in] the world for the evil things that they do; I will punish the wicked people for the sins that they have committed. I will stop arrogant/proud people from being proud, and I will stop ruthless people from acting cruelly.
Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀, àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
12 [And because I will cause most people to die], people will be harder to find than gold, harder to find than fine gold from Ophir [in Arabia].
Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn ju ojúlówó wúrà lọ, yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
13 I will shake the sky, and the earth will [also] move out of its place. That will happen when [I], the Commander of the armies of angels, punish [wicked people], when [I show them that] I am extremely angry [with them].
Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì; ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀ láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.
14 And all [the foreigners in Babylon will run around] like [SIM] deer that are being hunted, like sheep that do not have a shepherd. They will try to find other people from their countries, and [then] they will escape [from Babylon] and return to their own countries.
Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
15 Anyone who is captured [in Babylon] will be killed by [their enemies’] swords [DOU].
Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu, gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
16 Their little children will be dashed to pieces on the rocks while [their parents] watch; [their enemies] will steal everything valuable from their houses and will rape their wives.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn, gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.
17 Look! I am going to incite the people of Media to attack Babylon. The [army of Media] will attack Babylon, even if they are offered [DOU] silver or gold [if they promise to not attack it].
Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn, àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
18 [With] their arrows, the [soldiers of Media] will shoot the young men [of Babylon]; they will not [even] act mercifully [DOU] toward infants or children!”
Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀; wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé tàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.
19 Babylon has been a very beautiful [MTY] city; [all] the people of Babylonia have been very proud of Babylon, [their capital city]; [but] God will destroy Babylon, like [SIM] he destroyed Sodom and Gomorrah.
Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
20 No one will ever live in Babylon again. It will be deserted forever. (Nomads/People who travel from place to place to live) will refuse to set up their tents there; shepherds will not bring their flocks of sheep to rest there.
A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran; ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́, olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
21 Instead, animals that live in the desert will be there; jackals/wolves will live in [the ruins of] the houses. Owls (OR, Ostriches) will live in [the ruins], and wild goats will romp/jump around [there].
Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀, àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn, níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
22 Hyenas will howl in the [ruined] towers, and jackals/wolves will make their dens in [the ruins of] the palaces that [were previously] very beautiful. The time when [Babylon will be destroyed] is very near; Babylon will not exist much longer.
Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn, àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.