< Genesis 34 >
1 One day Dinah, the daughter of Jacob and Leah, went to visit some of the women in that area.
Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
2 Shechem, one of the sons of Hamor, the ruler of that area who was descended from the Hiv people-group, saw her. He wanted her. So he grabbed her and forced her to have sex [EUP] with him.
Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
3 He [SYN] was very much attracted to her, and fell in love with her, and he tried to get her to love him.
Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
4 So Shechem said to his father Hamor, “Please get this girl for me. I want her to become my wife!”
Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
5 Jacob very soon found out that his daughter Dinah had been disgraced/defiled. But his sons were in the fields with his livestock, so he did nothing about it until they returned home.
Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
6 In the meantime, Shechem’s father Hamor went to talk with Jacob.
Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
7 While they were still talking, Jacob’s sons came in from the field. When they found out what had happened, they were shocked and very angry. They said, “Shechem has done something that is very disgraceful among us Israeli people, something that never should be done!”
Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
8 But Hamor said to them, “My son Shechem really likes this girl. Please allow him to marry her.
Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
9 Let’s make an agreement: You will give your daughters to our young men to be their wives, and we will give our daughters to your young men to be their wives.
Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
10 You can live among us, and live anywhere in our land that you wish. You can buy and sell things (OR, travel around) and if you find land that you want, then you can buy it.”
Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
11 Then Shechem said to Dinah’s father and brothers, “If you feel good toward me and do what I am asking for, I will give you whatever you ask for.
Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
12 Tell me what gifts you want and what bride price you want, and I will give you what you ask for. I just want you to give the girl to me to be my wife.”
Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
13 But because Shechem had done a shameful thing to their sister Dinah, the sons of Jacob deceived Shechem and his father Hamor
Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
14 by saying to them, “No, we cannot do that. We cannot give our sister to be the wife of a man who is not circumcised, because that would be a shameful thing for us to do.
Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
15 We will do that only if you do one thing: You must become like us by circumcising all the males that are among you.
Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
16 Then we will give our daughters to your young men to be your wives, and we will take your daughters to be the wives of our young men. We will live among you, and we will become one people-group.
Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
17 But if you will not agree to being circumcised, we will take our sister and go back to our land.”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
18 What they said pleased Hamor and his son Shechem.
Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
19 Shechem was very much in love with Jacob’s daughter, so he quickly agreed to do what they suggested.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
20 Shechem went with Hamor to the meeting place near the city gate, and they spoke to the city leaders, saying,
Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
21 “These men are friendly toward us. We should let them live here and travel around (OR, buy and sell things) and if they find land that they want, they can buy it. There is plenty of land for them to live here. Our young men can marry their daughters, and their young men can marry our daughters.
Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 But these men will agree to live among us and become one people-group with us only if all our males are circumcised, as they are.
Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
23 But if we do that, just think! Their livestock and their possessions and their other animals will become ours [RHQ]! So we should agree to do what they suggest, and then they will live among us!”
Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
24 Shechem was the most respected person in his father’s household, so all the men who were there at the city gate agreed to what Hamor and Shechem suggested. So every male in the city was circumcised.
Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 On the third day after that, when the men of the city were still sore because of being circumcised, two of Jacob’s sons, Simeon and Levi, who were Dinah’s brothers, took their swords and entered the city without anyone opposing them, and killed all the men.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 They even killed Hamor and his son Shechem. Then they took Dinah out of Shechem’s house and left the city.
Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 Then the other sons of Jacob went into the city where all those dead bodies were. They (looted/took everything in) the city to get revenge for the shameful thing that had been done to their sister.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
28 They took away the people’s sheep and goats, their cattle, their donkeys, and everything else that they wanted from inside the city and from out in the countryside.
Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
29 They took away everything that was valuable, even the children and the women. They seized and took away everything that was in the houses.
Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
30 Then Jacob said to Simeon and Levi, “You have caused a lot of trouble for me! Now the Canaan people-group and the Perizzi people-group and everyone else who lives in this land will (hate me/say my name stinks)! I do not have many men to fight for us, so if they all gather together and come to me and attack us, they will destroy us and all our household!”
Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
31 But they replied, “(Should we have allowed Shechem to treat our sister like a prostitute?/We could not just let Shechem treat our sister like a prostitute!)” [RHQ]
Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”