< Genesis 3 >
1 The snake was more cunning than all the other wild animals that Yahweh God had made. [One day Satan gave to] the snake [the ability to talk to the woman]. The snake said to her, “Did God really say to you, ‘Do not eat the fruit from any of the trees in the park/garden’?”
Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”
2 The woman replied, “[What God said was], ‘Do not eat the fruit from the tree that is in the middle of the park/garden or touch it. If you do that, you will die. But you can eat fruit from any of the other trees.’”
Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà,
ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’”
4 The snake said to the woman, “No, you will certainly not die. God said that
Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.”
5 [only] because he knows that when you eat fruit from that tree, [you will understand new things. It will be as though] your eyes are opened [MET], and you will know what is good [to do] and what is evil [to do], just as God does.”
“Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”
6 The woman saw that the fruit on that tree was good to eat, and it was very beautiful, and she desired it because [she thought] it would make her wise. So she picked some of the fruit and ate it. Then she gave some to her husband, and he ate it.
Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́.
7 Immediately [it was as though] their eyes were opened, and they realized that they were naked, so they were ashamed. So they [picked] some fig leaves and fastened them together to make clothes for themselves.
Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.
8 [Late that afternoon], when a cool breeze was blowing, they heard the sound/footsteps of Yahweh as he was walking in the park/garden. So the man and his wife hid themselves among the bushes in the park/garden, [so that Yahweh God would not see them].
Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà.
9 But Yahweh God called to the man, saying to him, “Why are you [trying to hide from me]?”
Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”
10 The man replied, “I heard the sound of your [footsteps/walking] in the garden, and I was naked, so I was afraid and I hid myself.”
Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”
11 God said, “How did you find out you were naked [RHQ]? It must be because you ate some of the fruit [from the tree] that I told you, ‘Do not eat its fruit.’” [RHQ]
Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”
12 The man said, “You gave me this woman to be with me. She is the one who gave me some of the fruit from that tree, and so I ate it.”
Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”
13 Then Yahweh God said to the woman, “Why did you do such a thing?” The woman replied, “I ate some of the fruit because the snake deceived me.”
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”
14 Then Yahweh God said to the snake, “Because you did this, of all the livestock and the wild animals, I will curse/punish you alone. As a result, you [and all other snakes] will scurry across the ground on your bellies, and so what you eat will have dirt [on it] as long as you live.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí, “Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ! Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́, ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
15 And I will cause you and the woman to act in a hostile way toward each other, and I will cause your brood and her descendants to act hostilely toward each other. You will strike at the heel [of one descendant] of hers, but he will strike your head.”
Èmi yóò sì fi ọ̀tá sí àárín ìwọ àti obìnrin náà, àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà; òun yóò fọ́ orí rẹ, ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”
16 Then Yahweh said to the woman, “You will have great pain when you give birth to children; you will suffer great pain as your children are being born [DOU]. You will greatly desire your husband [to show affection for you], but he will rule over you.”
Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé, “Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ; ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ. Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí, òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”
17 Then Yahweh said to the man, “You heeded what your wife said, and you ate some of the fruit [of the tree] concerning which I commanded you saying, ‘Do not eat it.’ So I will make it difficult [to grow things in] the ground because of what you did. You will have to work hard as long as you live to produce things from the ground to eat.
Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’ “Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ; nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
18 Thornbushes and thistle plants and other weeds will grow [and prevent what you have planted from growing]. And for food, you will have to eat things that just grow in your fields.
Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ, ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.
19 [All your life] you will sweat as you work hard to produce food to eat. Then you will die [EUP], and your [body will be buried] in the ground. [I made] you from soil, so when you [die and are buried your body will decay] and become soil again.”
Nínú òógùn ojú rẹ ni ìwọ yóò máa jẹun títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀, nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá; erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ, ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”
20 [The man, whose name was] Adam, named his wife Eve, [which means ‘living’], because she became the ancestor of all living people.
Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.
21 Then Yahweh God [killed some animals and] made clothes from their skins for Adam and his wife.
Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n.
22 Then Yahweh said, “Look! Those two have become like us because they know what is good [to do] and what is evil [to do]. So now, it will not be good if they reach out and pick and eat [some of the fruit from] the tree [which enables people who eat it] to live [forever]!”
Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.”
23 So Yahweh God expelled the man and his wife from the garden of Eden. Yahweh God had created Adam from the ground, but now he forced him to till that ground [so that he could grow food to eat].
Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá.
24 After Yahweh expelled them, on the east side of the garden he placed (cherubim/creatures with wings) and [an angel holding] a flaming sword which flashed back and forth. He did that in order to block the entrance to the garden, so that people could not go back to the tree that enables people [who eat its fruit] to live [forever].
Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.