< Ezekiel 6 >

1 Yahweh gave me another message. He said,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
2 “You human, turn toward the mountains of Israel, and prophesy [what will happen to] them, and say,
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3 ‘You mountains and hills of Israel [APO], listen to what Yahweh the Lord says to you: “I am about to [enemy soldiers with] swords to come and destroy [the shrines on] your hilltops.
wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
4 They will smash all the [for worshiping idols] and the altars for burning incense. And they will [many Israeli] people in front of those idols.
Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
5 Their corpses will lie in front of their idols, and their bones will be scattered around their altars.
Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
6 Wherever the Israelis live, their towns will be ruined, and the shrines where they worship idols will be smashed. Their altars will be completely smashed [DOU], their idols will be completely smashed [DOU], and everything that they own will become a pile of ruins.
Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
7 Many of their people will be killed; and then they will know that I, Yahweh, [have the power to do the things that I say that I will do].
Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 But I will allow some of the Israelis to remain alive. They will escape being killed when their enemies scatter them among many other nations.
“‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
9 When that happens, in those nations to which they have been forced to go, those who have escaped from being killed will think about me. They will remember that I was very grieved because of their turning away from me [IDM] with their inner beings, and because they very much desired [IDM] to worship their idols. They will (hate/be very displeased with) themselves because of the evil and detestable things that they have done.
Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
10 [they will realize that] I, Yahweh, [have punished them. They will realize that] when I threatened to punish them, I surely intended [LIT] to do that.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
11 So this is what I, Yahweh the Lord, [to you, Ezekiel]: ‘Wring your hands and stamp your feet and cry [to show that you are distressed], and [about what will happen to] your Israeli people [MTY] because of all their wicked and detestable behavior. They will be killed [their enemies’] swords, they will die from hunger, and they will die from plagues.
“‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
12 Those who are far [from Jerusalem] will die from plagues, those who are close [to Jerusalem] will be killed by [their enemies’] swords, and those who are still alive will die from hunger. That is how I will punish [MTY] them.
Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
13 [Some of] your people’s corpses will lie among their idols around their altars, on every high hilltop and on all the mountaintops, under every big tree [DOU]—at all the places where they burned incense [honor] their idols. Then they will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
14 And I will stretch out my arm and cause your entire country to become an empty wasteland, from the [in the far south] to [town in the far north]. Then they will realize that I, Yahweh, [have the power to do the things that I say that I will do].’”
Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ezekiel 6 >