< Ezekiel 28 >
1 [Then] Yahweh gave me another message. [He said]:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 “You human, give to the king of Tyre this message from [me], Yahweh the Lord: ‘You have very proudly claimed, “I am a god! I sit on a throne of a god [in a city on an island] in the sea!” You boast that you are a god; but you are only a man, not a god.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
3 [You think that] you are wiser than Daniel was, [and you think that] you can understand every secret.
Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
4 By being wise and understanding [a lot], you have become [very] rich; you have acquired much gold and silver for your treasuries.
Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
5 [Yes, it is true that] by trading wisely, you have been enabled to become very rich, and because you are rich, you have become very proud.
Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
6 Therefore, this is what Yahweh the Lord says: “Because you think that you are as wise as a god,
“‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
7 I will [now] bring a foreign [army] to attack your [country], an army that causes other nations to be terrified. They will pull out their swords to strike you, [you who think that] [IRO] you have marvelous/great wisdom, and they will destroy all your beautiful things.
Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8 They will bring you down to your grave; you will die violently like [MET] those who died in the sea.
Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
9 Then you will certainly not [RHQ] say to those who are killing you, 'I am a god!' [because they will know that] you are not a god; you are only a man.
Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
10 You will die like other people who are unacceptable to me die, killed by foreigners.” [That will surely happen because] I, Yahweh, have said it.’”
Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
11 Yahweh also gave me this message:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12 “You human, sing a sad/funeral song about the king of Tyre. Say to him, ‘This is what Yahweh the Lord says: [“You thought that] [IRO] you were completely perfect, extremely wise and handsome.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
13 You [had a wonderful life, as though] you were in my [beautiful] garden in Eden. Your [clothes] were decorated with many [HYP] kinds of very valuable stones— ruby, topaz, emerald, chrysolite, onyx, jasper, turquoise, and beryl [stones]. Those stones were set/placed in gold [mountings]. They were prepared for you on the day that you were born.
Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14 I appointed [DOU] you to be like [MET] a strong angel to guard the people. [It was as though I put] you on my holy mountain, and you walked among fiery stones.
A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
15 You were completely good in all that you did, from the day that you were created/born, until you [started to] do wicked things.
Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16 [Then] you became busy trading things, and you started to act violently, and you sinned. So I caused you to be disgraced; and the angel who was guarding you forced you to leave my holy mountain, forced you to leave your place among those fiery stones.
Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
17 You were extremely proud because you were very handsome. Because you loved beautiful things, you did things that wise people do not do. [So] I threw you to the ground, and allowed [other] kings who saw you to laugh at you.
Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
18 By committing many sins and by trading things dishonestly, you caused your places of worship to become unacceptable to me. So I caused a fire [to burn down your city]. [Your city] was burned completely; the people who were watching it saw that only ashes remained on the ground.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
19 All the people who knew what your [city was like previously] were appalled. Now [your city] has disappeared, and it will not exist any more.”’”
Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
20 [Then] Yahweh gave me another message. [He said],
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
21 “You human, turn toward Sidon [city], and declare the terrible things that will happen to it.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
22 Give [the people of Sidon] this message from [me], Yahweh the Lord: ‘I am your enemy, [you people of] Sidon, and by what I do to you, I will reveal that I am very great/glorious. When I punish you and reveal that I am holy, everyone who is watching that will know that it is I, Yahweh, [who have the power to do what I say that I will do].
kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
23 I will send a plague upon you, and I will send [enemies to come and] kill [MTY] you in your streets. They will attack you from every direction, and your people will be slaughtered inside the walls of your city. Then everyone will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].'
Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
24 No longer will those who live near you people of Israel [hurt you] like [MET] painful briers and sharp thorns [hurt people]. And then the Israeli people will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].”
“‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
25 And this is [also] what Yahweh the Lord says: “Some day the people of Israel will live in their own land [again], the land that I gave to Jacob, who [also] served me. I will gather them from [distant] countries where I have scattered them. And I will reveal to the nations that I am holy among my people.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
26 My people will live safely in Israel; they will build houses and plant vineyards. And when I punish the nearby nations that despised them, they will know that it is I, Yahweh their God, [who has done it].”
Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”