< Ezekiel 21 >
1 Yahweh gave me another message. [He said, ]
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
2 “You human, turn toward Jerusalem. Preach about what will happen to the temple [there]. Preach about what will happen to the Israeli people.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
3 Say to them, ‘This is what Yahweh says: I am opposed to you.
Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
4 [what I will do to you will be as though] [MET] I will pull my sword from its sheath [and strike you]. I will kill everyone, including righteous people and wicked people [DOU]. I will get rid of everyone, from the south to the north.
Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
5 Then everyone will know [it is as though] I, Yahweh, have struck people with my sword, and I will not put it back in its sheath again.’
Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
6 Therefore, you human, groan! Groan in front of the Israeli people very sadly and sorrowfully [IDM, DOU].
“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
7 And when they ask you, ‘Why are you groaning?’ tell them, ‘Because of the news that they soon will hear. Everyone will be very fearful [IDM], and their knees will become as weak as [SIM] water. [A great disaster] will soon occur. That is what Yahweh the Lord is promising.’”
Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
8 Yahweh gave me another message. [He said],
Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
9 “You human, prophesy and say [to them], ‘This is what Yahweh says: I have sharpened my sword and polished it.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
10 It is sharpened in order that I can [many people with it]; it is polished so that it will flash like lightning. The people of Judah will not [their being punished like this], but they did not repent [I only struck them] with a stick.
a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
11 A sword should be polished, and be grasped [in someone’s hand]. It should be sharpened and polished, ready for someone to use it to kill people.
“‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
12 [So, ] you human, cry and wail, because I will use my sword to kill my people, including the leaders of Israel. They and all the other people, my people, will be killed by swords, so beat your [to show that you are sad].
Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
13 I am about to test my people, and the kings [MTY] of Judah will not escape being punished. That is what I, Yahweh the Lord, say.
“‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
14 So, you human, prophesy; clap your [to show that you are very happy about what is going to happen]. My sword will strike them again and again; it is a sword for slaughtering many people, while I attack them from every side.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
15 In order that people will be very much afraid [IDM] and many people will be killed, I have [soldiers holding] my swords at every [city] gate, ready to slaughter people. Those swords will flash like lightning, as the [soldiers] grasp them to slaughter people.
Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
16 Their swords [APO] will slash to the right and [then] to the left, whichever way they turn the blades.
Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
17 Then I will clap my [triumphantly]; and [then] I will no longer be angry. [That will surely happen because] I, Yahweh, have said it.’”
Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
18 Yahweh gave me another message. [He said, ]
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
19 “You human, [a map], and on it mark two roads for the King of Babylonia to march [along with his army, carrying] their swords. When they depart from their country, they will come to a sign post where the road divides.
“Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
20 [If they continue on the one road, ] they will attack [city], the capital of the Ammon people-group. [If they continue on the other road, ] they will come to Judah and to Jerusalem, [a city] with walls around it.
La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
21 [When the army of] Babylonia comes to where the road divides, [they will stop], and the king will perform magic rituals [to decide which road to go on]. He will throw arrows; [then] consult his [about which road to go on], and he will (examine/look at) the [of a sheep].
Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
22 With his right hand he will pick up the arrow marked ‘Jerusalem’. He will [command his soldiers to go to Jerusalem. When they arrive there, they] will set up (rams/devices to [down the walls], ) and [then] the king will give the command for them to slaughter [the people]. They will shout [a battle-cry], and they will set up the rams against the [city] gates. They will build a dirt ramp [against the walls around the city], and set up things to bash those walls.
Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
23 The [in Jerusalem] who had promised [to be loyal to the King of Babylonia will think that those rituals must be wrong. They will think that his army should not be attacking them]. But he will remind them of the sins [MTY] that they had committed, [his army] will capture them.
Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
24 Therefore, [tell the Israeli people that] this is what Yahweh the Lord says: ‘You people have allowed everyone to see that you are openly [against the King of Babylonia], and by doing that you have shown that everything that you do is sinful. Therefore you will be captured and [to Babylonia].’
“Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
25 Also, say, ‘You very wicked [DOU] king of Israel, it is your [to die]. It is the time for you to be punished.’
“‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
26 And this is what Yahweh the Lord says [to you soldiers from Babylonia]: ‘Take off [the king’s] turban and his crown, because now things will be different than they were [before]. [in Jerusalem] who had no authority will now be given authority, and those who had authority will have their authority taken from them.
èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
27 [Jerusalem] will be completely ruined. I will cause it to be ruined, and it will not be rebuilt/restored until the king to whom the city truly belongs comes; I will give it to [to rule it].’”
Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
28 “And, you human, prophesy and say [this]: 'This is what Yahweh the Lord says about the Ammon people-group, and about what they have said to insult [Israel]: [“The King of Babylon says, ] ‘[My soldiers have] swords’ [APO]; they have pulled out those swords to slaughter many people. They have polished them in order to kill people, and to make those swords flash like lightning.
“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 [Your prophets] have given you false visions about [what will happen to] you, and they have given you messages that are not true. So swords will strike the necks of those wicked people; it is time for them to be killed; it is the day when they will be [for their sins].
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
30 You must put your swords back in their sheaths [because the days for you to slaughter your enemies are ended]. I will judge those people in the country where they were born.
“‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 I will pour out my punishment [MTY] on them. Because I am very angry with them, my breath on them will scorch them [like] fire [MET]. I will allow brutal men to capture them, men who are experts in killing people.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
32 You will be [like] fuel [MET] [that is burned] in a fire. Your blood will be shed in your own land. No one will remember you any more. [That will surely happen because] I, Yahweh, have said it.” '”
Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”