< Ezekiel 14 >

1 One day some of the elders of Israel came to me and sat down in front of me.
Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
2 Then Yahweh gave me this message:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
3 “You human, these men want to [IDM] worship idols, and they are allowing idols to induce them to sin [IDM]. So I will certainly [RHQ] answer them if they ask me for advice.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
4 So say this to them: ‘This is what Yahweh the Lord says: When any Israeli person wants to worship idols which will induce him to sin, and he goes to a [to get advice], I, Yahweh, will give him the answer that he deserves to receive because he worship idols.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
5 [I will do that] in order that the Israeli people, who have abandoned me in order to worship their idols, will sincerely [IDM] worship me again.’
Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
6 Therefore, say to the Israeli people, ‘This is what Yahweh the Lord says: (Repent/Stop sinning)! Stop worshiping your idols, and stop all your [other] detestable behavior!’
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
7 When any of [you] Israeli people or any foreigner living among you turns away from me and starts worshiping idols [IDM] that induce him to sin, and then goes to a prophet to find out what I want him to do, I myself will answer him.
“‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
8 I will show that I detest him, and [what happens to] him to be a warning [to others], and cause him to be someone whom people despise. I will cause him to no longer be allowed to associate with my people. Then you will know that I, Yahweh, [have the power to do what I say that I will do].
Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
9 And if a prophet is deceived and gives a false prophecy, [even though] I [allowed him to] give that message, I will get rid of him and remove him from among my Israeli people.
“‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
10 Both the prophet and the one who asks him for advice will be guilty, [and I will punish both of them].
Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Then you Israeli people will no longer abandon me, and you will no longer become unacceptable to me because of your sins. You will be my people, and I will be your God. [That is what I], Yahweh the Lord, say.”
Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
12 Yahweh gave me another message. [He said],
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
13 “You human, [the people of some] country sin against me by abandoning me, and I punish [IDM] them by cutting off their food supply and by sending a famine, with the result that people and animals die,
“Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
14 even if Noah, Daniel, and Job were there, they would save only themselves because of their being righteous. [That is what I], Yahweh the Lord, declare.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
15 Or, if I send wild animals throughout the country, and they attack and [many of] [HYP] the people, with the result that travel in that country becomes very dangerous and no one travels through that country,
“Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
16 [as surely] as I am alive, even if those three men were in that country, they could not save [even their own] sons or [from being killed]. Only those [three] would (be saved/remain alive), and the country would become desolate. [That is what I], Yahweh the Lord, declare.
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
17 Or, if I bring enemy soldiers [MTY] to attack that country, and they kill [MTY] people and animals throughout that country with their swords,
“Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
18 as surely as I am alive, even if those three men were in that country, they would not be able to save even their own sons or [from being killed]. They would save only themselves. That is what I, Yahweh the Lord, declare.
Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
19 Or, if I send a plague into that land and cause the people and the animals to [from the plague] because I am very angry with those people,
“Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20 [as surely] as I am alive, even if Noah, Daniel and Job were in that country, they would not [be able to] save even their sons and daughters. They would save only themselves because of their being righteous. [That is what I], Yahweh the Lord, declare.
bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
21 So [now] this is what [I, ], Yahweh the Lord, say: I will cause four things to happen to [the people of] Jerusalem to punish them very severely. [Some] people and animals will be killed by swords, [some will die from] famines, [others will be attacked and killed by] wild animals, and [others will die in] plagues.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22 But some [of your people] will remain alive, [both adults] and children. They will come to you, [Ezekiel, in Babylon]. And when you see [disgusting] behavior and actions, you will realize that I had good reasons for causing [the people of] Jerusalem to experience those many great disasters [DOU] that I have sent to them.
Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23 When you see those things that they do, you will know that there were very good reasons [LIT] for me to do everything that I caused to happen to them. [That is what I], Yahweh the Lord, declare.”
Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ezekiel 14 >