< Exodus 34 >
1 Yahweh said to Moses/me, “Cut two slabs of stone that will be like the first slabs, the ones that you broke. Then I will engrave on them the words that were on the first slabs.
Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, Èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn.
2 Get ready tomorrow morning, and come up to the top of Sinai Mountain again to talk with me there.
Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà.
3 Do not allow anyone to come up with you. I do not want anyone [else] to be anywhere on the mountain. Do not allow any sheep or cattle to graze (at the base of/near) the mountain.”
Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”
4 So Moses/I cut two slabs of stone that were like the first ones. He/I arose early the next morning. He/I took the slabs and carried them in his/my hands up to the top of Sinai Mountain, as Yahweh had commanded.
Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀.
5 Then Yahweh descended in the [tall] cloud and stood with Moses/me there. He proclaimed that it was he, Yahweh, [who was going to speak to Moses/me].
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa.
6 Then Yahweh passed in front of him/me and proclaimed, “I am Yahweh God. I always act mercifully and kindly [toward people]. I do not get angry quickly. I [truly] love [people] and I do what I promise to do for them, without changing.
Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, Ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́,
7 I love people for thousands of generations. I forgive people for all kinds of sins [TRI]. But I will certainly punish [LIT] those who are guilty. I will punish not only them, but I will punish (their descendants, down to the third and fourth generation/their children and grandchildren and great-grandchildren).”
Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún, ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”
8 Moses/I quickly prostrated himself/myself on the ground and worshiped [Yahweh].
Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.
9 He/I said, “Yahweh, if you are now pleased with me, I ask that you go with us. These people are very stubborn [IDM], but forgive us for all our sins [DOU], and accept us to be people who belong to you [forever].”
Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”
10 Yahweh replied, “Note this: I am going to make a solemn agreement [with the Israeli people]. As they are watching, I will perform great miracles. They will be miracles that no one has ever done on the earth in any nation. All the people who are near you will see the great things that I, Yahweh, will do. I will do awesome things for you [all].
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ Èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí Èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó.
11 [Each Israeli] person must obey what I am commanding you this day. Do not forget that [if you obey me], I will expel the Amor, Canaan, Heth, Periz, Hiv, and Jebus people-groups [from the land]. But be careful that you do not make any [peace] agreements with any of the people who live in the land into which you are going, because if you do that, [you will begin to do the evil things that they do]. It will be [like] falling into a trap.
Ṣe ohun tí Èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ.
Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ.
13 You must tear down their altars, destroy their sacred pillars, and cut down [the poles that they use to worship their female goddess] Asherah.
Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn.)
14 You must worship only me, [and] not worship any other god, because I, Yahweh, cannot endure any rivals.
Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.
15 Do not make peace agreements with [any group] that lives in that land. When they worship their gods and offer sacrifices to their gods, and they invite you to join them, do not join them. If [you join them], you will eat the food that they sacrifice to their gods, and [you will not be faithful to me. You will be like people who] commit adultery, [who are not being faithful to their spouses] [MET].
“Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn.
16 If you take some of their women to be wives for your sons, and these women worship their own gods, they will persuade your sons also to worship their gods.
Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
17 Do not pour melted metal into molds to make statues for you to worship.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.
18 [Each year], during the month [of/named] Abib, celebrate the Festival of Eating Bread Made Without Yeast. [During that festival], for seven days you must not eat bread made with yeast, as I commanded you, because it was in that month that you left Egypt.
“Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí Èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.
19 Your firstborn sons and the firstborn [male] animals of your cattle and sheep [and goats] belong to me.
“Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn.
20 The firstborn of your [male] donkeys [also belong to me]. But you may buy them back by [offering to me] lambs [in their place]. If you do not do that, you must [kill these animals by] breaking their necks. You must also buy back your firstborn sons. You must bring an offering to me [LIT] each time you come to [worship] me.
Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.
21 [Each week] you may work for six days, but on the seventh day you must rest. [Even] during the times when you plow [the ground] and harvest [your crops], you must rest [on the seventh day].
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.
22 [Each year] celebrate the Harvest Festival, when you begin to harvest the first crop of wheat, and also celebrate the Festival of Living in Temporary Shelters, when you finish harvesting [the grain and fruit].
“Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún.
23 Three times each year all the men must come to worship me, Yahweh, the God of the Israeli people.
Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli.
24 I will expel the people-groups that live in the land [where you will be], and I will cause your territory to become very large. As a result, no group will try to conquer your country if you come to worship me each year during those three festivals.
Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, Èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
25 When you sacrifice an animal [MTY] to me, do not offer with it bread that is made with yeast. And during the Passover Festival, when you sacrifice lambs, do not keep any of the meat until the next morning.
“Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.
26 I am Yahweh God. You must bring to my Sacred Tent the first part of the grain that you harvest each year. When you kill a young animal/kid [either a lamb or a calf], do not [prepare to eat it by] boiling it in its mother’s milk.”
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”
27 Yahweh also said to Moses/me, “Write down the words that I have told you. By giving you these commands, I have made a solemn agreement with you and with the [other] Israeli people.”
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.”
28 Moses/I was there [on the top of the mountain] with Yahweh for 40 days and nights. During that time he/I did not eat or drink anything [SYN]. He/I engraved on the stone slabs the words of the Ten Commandments, [which were part of Yahweh’s] solemn agreement.
Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.
29 When Moses/I came back down the mountain, carrying in his/my hand the two stone slabs on which were written the Ten Commandments, his/my face was shining because he/I had been talking with Yahweh, but he/I did not know that his/my face was shining.
Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀.
30 When Aaron and the [other] Israeli people saw Moses/me, they were amazed/surprised that his/my face was shining. So they were afraid to come near him/me.
Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn.
31 But Moses/I called to them. Then Aaron and the other Israeli leaders came to him/me, and he/I talked with them.
Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀.
32 Afterwards, all the other Israeli people came near, and he/I told them all the laws that Yahweh had given to him/me on Sinai Mountain.
Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.
33 When Moses/I finished talking to the people, he/I put a veil over his/my face.
Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀.
34 But whenever Moses/I entered the Sacred Tent to talk with Yahweh, he/I removed the veil. When he/I came back out, he/I would always tell to the Israeli people everything that Yahweh had commanded him/me [to tell them].
Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un,
35 The Israeli people would see that Moses’/my face was [still] shining. Then he/I would put the veil back on his/my face again until the next time that he/I went into [the Sacred Tent] to talk with Yahweh.
àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.