< Exodus 23 >
1 “Do not tell to others (false rumors/untrue reports) about other people. Do not help someone who is guilty by (testifying falsely/lying) [about what happened].
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
2 Do not join a group of people who are planning to do something evil. Do not testify the way the [crowd wants you to], if that will prevent [the judge from deciding the case] justly/fairly.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
3 When a poor person is on trial, do not [testify in] his favor [just] because he is poor [and you feel sorry for him].
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
4 If you see someone’s bull or donkey when it is wandering away [loose], take it back to [its owner, even if the owner] is your enemy.
“Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
5 If you see someone’s donkey that has fallen down [because of its heavy load], help the owner to get the donkey up again, [even if] he is someone who hates you. Do not just walk away [without helping him].
Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
6 Decide the cases of poor people who are on trial [as] fairly [as you decide the cases of other people].
“Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
7 Do not accuse people falsely. Do not decide that innocent and righteous [DOU] people should be executed, because I will (punish/not forgive) people who do such an evil thing.
Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
8 Do not accept money that is a bribe, because officials who accept bribes are not able to [MTY] decide what is right to do, and they do not allow innocent people to be treated fairly.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
9 Do not mistreat foreigners [who live among you]. You know [how people often treat] foreigners, because the Egyptians [did not treat you well when] you were foreigners there.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Plant [seeds] in your ground and gather the harvest for six years.
“Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
11 But during the seventh year you must not plant anything. [If things grow without your planting seeds], allow poor people [to harvest and] eat the crops. If there are still crops (left over/that they do not harvest), allow wild animals to eat them. Do the same thing with your grapevines/vineyards and your olive trees.
Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
12 [You may] work for six days [each week], but on the seventh day you must rest [and not work]. And on the seventh day you must allow your work animals and your slaves and the foreigners [who live among you] also [to rest and] be refreshed.
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
13 Make certain that you obey everything that I have commanded [you to do]. Do not pray to [MTY] other gods. Do not even mention their names.”
“Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
14 “Every year you must celebrate three festivals to [honor] me.
“Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
15 [The first one] is the Festival of Bread That Has No Yeast. Celebrate it in the month [that is named] Abib. That is the month in which you left Egypt. Celebrate it in the way that I commanded you. And always bring [LIT] an offering when you come to worship me.
“Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
16 The second one is the Festival of Harvesting. During that festival you must offer to me the first parts/harvest of your crops that grow from the seeds that you planted. The third one is the Festival of Living in Temporary Shelters. That will be after you finish harvesting your grain and grapes and fruit.
“Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
17 Every year, at each of these times, all the men must gather together to worship me, Yahweh God.
“Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
18 When you sacrifice an animal [and offer it] to me, you must not offer bread that has been baked with yeast. [When you] offer sacrifices, [burn] the fat [from the animals on that same day]. Do not allow any fat to remain until the next morning.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
19 Each year, when you harvest your crops, bring to the place where you worship me, Yahweh God, the first part of what you harvest. When you kill a (young animal/kid [or lamb or calf)], do not [prepare to eat it by] boiling it in its mother’s milk.”
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
20 “Note this: I am going to send an angel ahead of you, to guard you as you travel and to bring you safely to the place that I have prepared [for you]. Pay attention to what he says and obey him. Do not rebel against him, because he will have my authority [MTY] and he will (punish/not forgive) [LIT] you if you rebel against him.
“Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
22 But if you pay attention to what he says and if you do all that I tell you [to do], I will fight strongly [DOU] against all of your enemies.
Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
23 My angel will go ahead of you, and will take you to where the Amor and Heth and Periz and Canaan and Hiv and Jebus people-groups live, and I will completely get rid of them.
Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
24 Do not bow down before their gods/idols or worship them. And do not do the things [that they think that their gods want] them to do. Completely destroy their gods/idols, and smash to pieces their sacred stones.
Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
25 You must worship me, Yahweh God. [If you do that], I will bless your (OR, bless [you by giving you]) food and water, and I will protect you from becoming sick.
Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
26 No women in your land will have (miscarriages/babies that will die after being born prematurely), and no women will be unable to become pregnant. And I will enable you to live a long time.
Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
27 I will cause the people who oppose you to become very afraid of me. I will cause the people whom you fight against to become very confused. And then I will cause them to turn around and run away from you.
“Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
28 I will cause your enemies to become terrified. And I will expel the Hiv, Canaan, and Heth people-groups from your land.
Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
29 I will not expel [all of] them in less than one year. If I did that, your land would become deserted, and there would be very many wild animals ([that would attack you/you would not be able to control]).
Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
30 I will expel those people-groups slowly, a few at a time, until the number of your people increases and you are able to live everywhere in the land.
Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
31 I will cause the borders of your land to extend from the (Red Sea/Gulf of Aqaba) [in the southeast] to the Mediterranean Sea [in the northwest], and from the [Sinai] Desert [in the southwest] to the [Euphrates] River [in the northeast of the country]. I will enable you [MTY] to expel the people who live there, so that you will expel them as you occupy more of the country.
“Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
32 You must not make any agreement/treaty with those people or with their gods.
Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
33 Do not allow [those people] to live in your land, in order that they do not cause you to sin against me. If you worship their gods, [you will not be able to escape from worshiping them and sinning against me, just like someone caught] in a trap [is unable to escape] [MET].”
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”