< Ecclesiastes 11 >

1 Give generously to others [some of] the money [MET] that you have; if you do that, later you will get back an equal amount.
Fún àkàrà rẹ sórí omi, nítorí lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ìwọ yóò rí i padà.
2 Share some of what you have with (seven or eight/several) [others], because you do not know when you will experience a disaster, [and if you give some of what you have to others], [when you experience that disaster, they will kindly help you].
Fi ìpín fún méje, àní fún mẹ́jọ pẹ̀lú, nítorí ìwọ kò mọ ohun ìparun tí ó le è wá sórí ilẹ̀.
3 [It is always true that] when clouds are full of water, they pour rain on the earth. [Similarly], wherever a tree falls on the ground, that is where it will remain.
Bí àwọsánmọ̀ bá kún fún omi, ayé ni wọ́n ń rọ òjò sí. Bí igi wó sí ìhà gúúsù tàbí sí ìhà àríwá, níbi tí ó wó sí náà, ni yóò dùbúlẹ̀ sí.
4 If farmers see in what direction the wind is blowing, they will know whether it is wise at that time to plant things or not. [It is also true that] if farmers look at the clouds [and see that they are blowing from the west, which means that it will probably rain, ] they will not [try to] harvest their crops on that day.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo afẹ́fẹ́ kò ní fúnrúgbìn; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo àwọsánmọ̀ kò ní kórè.
5 We do not know where the wind comes from or where it goes, and we do not know how bodies are formed in women’s wombs. Similarly [SIM], God is the one who made everything, and we cannot [fully] understand what God does.
Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́ tàbí mọ bí ọmọ tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́run ẹlẹ́dàá ohun gbogbo.
6 [Start] planting your seeds in the morning, and do not stop planting them until the evening, because you do not know which ones will grow better, the ones you plant in the morning or the ones you plant later in the day, or whether both will grow well.
Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọlẹ̀ ní àṣálẹ́, nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rere bóyá èyí tàbí ìyẹn tàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákan náà.
7 It is very delightful to be alive and see [MTY] the sun [rise every morning].
Ìmọ́lẹ̀ dùn; Ó sì dára fún ojú láti rí oòrùn.
8 [Even] if people live for many years, they should enjoy all of them. But they should not forget that [some day they will die] and then they will never be able to see any light again, and we do not know what will happen to us after we die.
Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdún tí ó le è lò láyé ṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùn nítorí wọn ó pọ̀. Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.
9 You young people, be happy while you are still young. Enjoy [IDM] doing the things that you want to do. But do not forget that [some day] God will judge you concerning all the things that you do.
Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwe kí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ. Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹ àti ohunkóhun tí ojú rẹ rí ṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.
10 [So when you are young] [MTY], do not worry about anything, and do not pay attention to the pains that you have in your body, because we will not remain young and strong forever.
Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹ kí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrò nítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.

< Ecclesiastes 11 >