< Deuteronomy 22 >

1 “If you see some Israeli’s ox or sheep that has strayed away, do not act as though you did not see it. Take it back [to its owner].
Bí o bá rí màlúù tàbí àgùntàn arákùnrin rẹ tí ó ń sọnù, má ṣe ṣé àìkíyèsí i rẹ̀ ṣùgbọ́n rí i dájú pé o mú padà wá fún un.
2 But if the owner does not live near you, or if you do not know who the owner is, take the animal to your house. [It can stay with you] until the owner comes, searching for it. Then you must give the animal to him.
Bí ọkùnrin náà kì í bá gbé ní tòsí rẹ tàbí bí o kò bá mọ ẹni náà, mú un lọ ilé pẹ̀lú rẹ kí o sì fi pamọ́ títí yóò fi wá a wá. Nígbà náà ni kí o fi fún un.
3 You must do the same thing if you see a donkey, or a piece of clothing, or anything else that someone has lost. Do not refuse to do what you should do.
Ṣe bákan náà tí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ arákùnrin rẹ tàbí aṣọ ìlekè tàbí ohunkóhun rẹ̀ tí ó sọnù. Má ṣe ṣe àìkíyèsí i rẹ̀.
4 “And if you see a fellow Israeli’s donkey or cow that has fallen down on the road, do not act as though you did not see it. Help the owner to lift the animal up [so that it can stand on its feet again].
Bí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù arákùnrin rẹ tí o dùbúlẹ̀ sójú ọ̀nà, má ṣe ṣàìfiyèsí i rẹ̀, ràn án lọ́wọ́ láti dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀.
5 “Women must not wear men’s clothes, and men must not wear women’s clothes. Yahweh our God hates people who do things like that.
Obìnrin kò gbọdọ̀ wọ aṣọ ọkùnrin, tàbí kí ọkùnrin wọ aṣọ obìnrin, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó ṣe èyí.
6 “If you happen to find a bird’s nest in a tree or on the ground, and the mother bird is sitting in the nest on its eggs or with the baby birds, do not take the mother bird [and kill it].
Bí ìwọ bá ṣe alábòápàdé ìtẹ́ ẹyẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, bóyá lára igi tàbí lórí ilẹ̀, tí ìyá wọn sì jókòó lórí àwọn ọmọ, tàbí lórí àwọn ẹyin, má ṣe gbé ìyá pẹ̀lú àwọn ọmọ.
7 You are permitted to take the baby birds, but you must allow the mother bird to fly away. Do this in order that things will go well for you and that you will live for a long time.
Ìwọ lè gbé ọmọ, ṣùgbọ́n rí i dájú pé o jọ̀wọ́ ìyá lọ́wọ́ lọ, kí ó ba à lè dára fún ọ àti kí o lè ní ẹ̀mí gígùn.
8 “If you build a new house, you must put a (railing/low wall) around the edge of the roof. If you do that, and if someone falls off the roof [and dies], (you will not be guilty of causing that person to die/his death [MTY] will not be your fault).
Nígbà tí o bá kọ́ ilé tuntun, mọ odi yí òrùlé rẹ̀ ká nítorí kí o má ba à mú ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ wá sórí ilẹ̀ rẹ bí ẹnikẹ́ni bá ṣubú láti òrùlé.
9 “Do not plant any crop in the area where your grapevines are growing. If you do, you are not allowed to harvest the crops that you have planted or to harvest the grapes [to make wine from them].
Má ṣe gbin oríṣìí èso méjì sínú ọgbà àjàrà rẹ; bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, kì í ṣe èso oko tí o gbìn nìkan ṣùgbọ́n èso ọgbà àjàrà pẹ̀lú yóò bàjẹ́.
10 “Do not hitch together an ox and a donkey [for plowing your fields].
Ìwọ kò gbọdọ̀ fi akọ màlúù àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tulẹ̀ pọ̀.
11 “Do not wear clothing that is made by weaving together (wool and linen/two different kinds of thread).
Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun àgùntàn àti aṣọ funfun papọ̀.
12 “[Twist threads together to] make tassels and sew/fasten them on the four bottom corners of your cloak.
Kí o ṣe wajawaja sí etí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin aṣọ ìlekè rẹ.
13 “Suppose a man marries a young woman and has sex with her and later decides that he does not want her any more,
Bí ọkùnrin kan bá mú ìyàwó àti, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dùbúlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, kórìíra rẹ̀,
14 and he says false things about her, and claims that she was not a virgin when he married her.
tí ó ṣì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sì i, tí o sì fún un ní orúkọ búburú, wí pé, “Mo fẹ́ obìnrin yìí, ṣùgbọ́n nígbà tí mo súnmọ́ ọn. Èmi kò rí àmì ìbálé rẹ̀.”
15 If that happens, the young woman’s parents must take the sheet that was on the bed when that man and their daughter were married, which still has bloodstains on it, and show it to the elders of the city at the (gate of/central meeting place in) the city.
Nígbà náà ni baba ọmọbìnrin náà àti ìyá rẹ̀ yóò mú ẹ̀rí pé, ó ti wà ní ìbálé tẹ́lẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ìlú ní ẹnu-bodè.
16 Then the father of the young woman must say to the elders, ‘I gave my daughter to this man to be his wife. But now he says that he doesn’t want her any more.
Baba obìnrin náà yóò wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Mo fi ọmọbìnrin mi fún ọkùnrin yìí láti fẹ́ níyàwó, ṣùgbọ́n ó kórìíra rẹ̀.
17 And he has falsely said that she was not a virgin when he married her. But look! Here is what proves that my daughter was a virgin! Look at the bloodstains on the sheet where they slept the night that they were married!’ And he will show the sheet to the elders.
Ní ìsinsin yìí ó ti sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí i ó sì wí pé, ‘Èmi kò rí ọmọbìnrin rẹ kí ó wà ní wúńdíá.’ Ṣùgbọ́n níhìn-ín yìí ni ẹ̀rí ìbálé ọmọbìnrin mi.” Nígbà náà ni àwọn òbí rẹ̀ yóò fi aṣọ hàn níwájú àwọn àgbàgbà ìlú,
18 Then the elders of that city must take that man and whip him.
àwọn àgbàgbà yóò sì mú ọkùnrin náà, wọn yóò sì jẹ ní yà.
19 They shall require that he pay a fine of 100 pieces of silver and give the money to the father of the young woman, because the man caused an Israeli young woman to be disgraced. Also, that woman must continue to live with him; she is his wife. He is not allowed to divorce her during the rest of his life.
Wọn yóò sì gba ìtánràn ọgọ́rùn-ún ṣékélì owó fàdákà fún baba ọmọbìnrin náà, nítorí ọkùnrin yìí ti fi orúkọ búburú fún wúńdíá Israẹli. Yóò sì máa ṣe ìyàwó rẹ̀; kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ní gbogbo ayé e rẹ̀.
20 “But if what the man said is true, and there is nothing to prove that she was a virgin when he married her,
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀sùn náà bá jẹ́ òtítọ́ tí a kò sí rí ẹ̀rí ìbálé obìnrin náà,
21 they must take that young woman to the door of her father’s house. Then the men of that city must execute her by throwing stones at her. They must do that because she has done something in Israel that is very disgraceful, by having sex with some man [while she was still living] in her father’s house. By executing her like that, you will get rid of this evil practice among you.
wọn yóò mú wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé baba rẹ̀ níbẹ̀ sì ni àwọn ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò ti sọ ọ́ ní òkúta pa. Ó ti ṣe ohun ìtìjú ní Israẹli nípa ṣíṣe àgbèrè nígbà tí ó wà nílé baba rẹ̀. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín yín.
22 “If a man is caught while he is having sex with another man’s wife, both of them must be executed. By doing that, you will get rid of this evil practice in Israel.
Bí o bá rí ọkùnrin kan tí ó bá ìyàwó ọkùnrin mìíràn lòpọ̀, àwọn méjèèjì ní láti kú. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín Israẹli.
23 “Suppose in some town a man sees a young woman who is engaged/promised to be married to another man, and he is caught having sex with [EUP] her.
Bí ó bá ṣẹlẹ̀ wí pé ọkùnrin kan pàdé wúńdíá tí a ti fi fún ni láti fẹ́ láàrín ìlú tí ó sì lòpọ̀ pẹ̀lú u rẹ̀,
24 You must take both of them to the (gate of/central meeting place in) that town. There you must execute them both by throwing stones at them. You must execute the young woman because she did not shout for help even though she was in the town. And the man must be executed because he had sex [EUP] with someone who was already engaged/promised to be married. By doing that, you will get rid of this evil practice among you.
ìwọ yóò mú àwọn méjèèjì lọ sí ẹnu ibodè ìlú náà kí o sì sọ wọ́n ní òkúta pa nítorí ọmọbìnrin náà wà ní ìlú kò sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́, àti ọkùnrin náà nítorí ó ba ìyàwó ọkùnrin mìíràn jẹ́. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
25 “But suppose out in the open countryside a man meets a young woman who is engaged/promised to be married, and he rapes her. If that happens, only that man must be executed.
Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìgbẹ́ ní ó ti ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin kan ti pàdé ọmọbìnrin tí a ti fẹ́ ṣọ́nà tí o sì fi tagbára tagbára bá a ṣe, ọkùnrin náà nìkan tí ó ṣe èyí ni yóò kú.
26 You must not punish the young woman, because she did not do anything for which she deserves to be executed. This case is like when one man attacks another man [in the countryside] and murders him,
Má ṣe fi ohunkóhun ṣe ọmọbìnrin náà; kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó tọ́ sí ikú. Ẹjọ́ yìí rí bí i ti ẹnìkan tí a gbámú tí ó pa aládùúgbò rẹ̀.
27 because the man who raped her saw her when she was in the open countryside, and even though she called out for help, there was no one there who could rescue her.
Nítorí ọkùnrin náà rí ọmọbìnrin náà ní ìta ibodè, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọbìnrin àfẹ́sọ́nà kígbe, kò sí ẹnìkankan níbẹ̀ láti gbà á kalẹ̀.
28 “If a man rapes a young woman who is not engaged/promised to be married, if someone sees him while he is doing that,
Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin pàdé wúńdíá tí kò ì tí ì ní àfẹ́sọ́nà tí ó sì fi tipátipá bá a ṣe tí a gbá wọn mú.
29 that man must pay 50 pieces of silver to the young woman’s father, and he must marry her, because he forced her to have sex with him. He is not allowed to divorce her for the rest of his life.
Ó ní láti san àádọ́ta fàdákà fún baba obìnrin náà, nítorí tí ó ti bà á jẹ́. Kò lè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ó sì wà láààyè.
30 “man must not disgrace his father by having sex with any of his father’s wives.”
Ọkùnrin kò gbọdọ̀ fẹ́ ìyàwó baba rẹ̀; kò gbọdọ̀ sọ ìtẹ́ baba rẹ̀ di àìlọ́wọ̀.

< Deuteronomy 22 >