< Deuteronomy 16 >
1 “[Each year] honor Yahweh our God by celebrating the Passover [Festival] in the month of Abib [in early spring]. It was on a night in that month that Yahweh rescued your ancestors from Egypt.
Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
2 [In order to celebrate that festival], go to the place that Yahweh will choose [for you to worship him], and offer [there one young animal] from your cattle or your sheep to be the Passover sacrifice, to honor Yahweh [MTY].
Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
3 [When you eat the Passover meal], the bread that you eat must not have yeast in it. You must eat this kind of bread, which will be called the bread of suffering/misery, for seven days. This is to help you to remember all during the time that you are alive that when your ancestors left Egypt, [where they were suffering because they were slaves], they left very quickly. [They did not put in yeast and wait for the dough to swell up].
Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
4 [During that festival], you must not have any yeast in any house in your land for seven days. Furthermore, the meat [of the animals] that you sacrifice on the evening of the first day [of the Passover Festival must be eaten during that night]; do not allow any of it to remain until the next day.
Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
5 “To honor Yahweh our God, you must offer the Passover sacrifice only at the place that he chooses for you [to worship him]; do not offer that sacrifice in any other town in the land that Yahweh is giving to you. Offer that sacrifice when the sun is setting, at the same time of day that your ancestors [started to] leave Egypt.
Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
7 Boil [the meat] and eat it at the place [of worship] that Yahweh our God chooses. The next morning, you may return to your tents.
Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
8 Each day for six days the bread that you eat must have no yeast in it. On the seventh day, you must all gather to worship Yahweh our God. [It will be a day of rest]; you must not do any work on that day.”
Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
9 “[Each year], from the day that you start to harvest your grain, count seven weeks.
Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
10 Then, to honor Yahweh our God, celebrate the Harvest Festival. Do that by bringing to him an offering [of grain]. Yahweh has blessed you [by causing it to grow in your fields during that year]. If you had a big harvest, bring a big offering. If you had a small harvest, bring a small offering.
Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
11 [Each married couple] should be joyful in the presence of Yahweh. Their children, their servants, the descendants of Levi [who are in that town], and the foreigners, orphans, and widows [who are living among you], should also be joyful. Bring those offerings to the place of worship that Yahweh will choose.
Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
12 [“When you celebrate these festivals] by obeying these commands, remember that your ancestors were previously slaves in Egypt.”
Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
13 “[Each year], after you have threshed all your grain and pressed [the juice from] all your grapes, you must celebrate the Festival of [Living in Temporary] Shelters for seven days.
Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
14 [Each married couple] along with their children, their servants, the descendants of Levi [who are in that town], and the foreigners, orphans, and widows [who are living among you], should be joyful in the presence of Yahweh.
Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
15 Honor Yahweh our God by celebrating this festival for seven days in the place that Yahweh chooses [for you to worship him]. You should all be joyful, because Yahweh will have blessed your harvest and all the other work that you have done.
Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
16 “So, each year all of you Israeli men must gather [with your families] to worship Yahweh our God at the place that he will choose, [to celebrate three festivals]: The Passover Festival, the Harvest Festival, and the Festival of Living in Temporary Shelters. Each of you men must bring [LIT] an offering [for Yahweh to these festivals]
Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
17 in proportion to the blessings that Yahweh has given you [during that year].”
Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
18 “Appoint judges and other officials throughout your tribes, in all the towns [in the land] that Yahweh our God is giving to you. They must judge people fairly/justly.
Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
19 They must not judge unjustly. They must not favor one person more than another. The judges must not accept bribes, because if a judge accepts a bribe, even if he is wise and honest, it will be very difficult for him to judge fairly [IDM]; [he will do what the person who gave him the bribe wants him to do and declare that] the righteous/innocent people [must be punished].
Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
20 You must be completely fair and just [DOU], in order that you will enter and occupy the land that Yahweh our God is giving to you.”
Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
21 “When you make an altar to worship Yahweh our God, do not put next to it any wooden statue [that represents] the goddess Asherah.
Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
22 And do not set up any [stone] pillar [to worship any idol, because] Yahweh hates them.”
Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.