< Amos 8 >

1 Yahweh showed me [in a vision] a basket full of ripe fruit.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 He asked me, “Amos, what do you see?” I replied, “A basket of [very] ripe fruit.” He said, “That indicates that it almost the end for my Israeli people. I will not change my mind again about punishing them.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 [Soon, ] instead of singing in the temple, they will be wailing. There will be corpses everywhere [HYP]. So, remain silent (OR, Everyone will be silent). [These things will surely happen because] I, Yahweh, have said it!”
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 [It is as though] you people trample on needy people, and you destroy the poor people.
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 You habitually say, “We wish that [RHQ] the new moon [festival] would end soon, in order that [restrictions on doing business during the festival will be ended] and we can sell grain. We wish that the Sabbath would end soon, in order that we will again be permitted to sell our wheat”— and [when you sell it], you charge a big price for it, and you cheat people by using scales that do not weigh correctly.
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 You sell wheat that you have swept up from the floor, and as a result it is mixed with dirt. Those who are needy and poor [DOU] and who do not have money [to buy things], you cause them to become your slaves by buying them with the [small amount of] silver [with which you could buy] a pair of sandals!
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Yahweh has declared, “Although you are very proud of [being descendants] [MTY] of Jacob, I solemnly declare that I will not forget the [evil things] that you have done.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 [Because of those evil things], your country will certainly [RHQ] soon be shaken, and all of you will mourn. [It will be as though] it will repeatedly rise and fall like [SIM] the Nile [River] that gets full of water [and overflows it banks] and then settles back into its riverbed.
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 On the day [when I punish my people], I will cause the sun to set at noontime, and the [entire] earth will be dark in the daytime.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 I will cause your [religious] celebrations to become times when you mourn; instead of singing, everyone will be weeping. Because of what I [will do], all of you will wear rough sackcloth and shave your heads [to show that you are sorrowing]. I will cause that time to be like when people mourn after an only son [has died]. All of you will be extremely sad all of that day.”
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 And Yahweh our God says this: “It will [soon] be the time when I will cause something to be very scarce [MET] throughout the country. But it will not be a time when there is no food or water; it will instead be a time when there will be no messages from me for anyone to hear.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 People will stagger from the [Dead] Sea to the [Mediterranean] Sea, and wander from the north to the east, searching for a message from me, but there will not be any.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 At that time, even beautiful young women and strong young men will faint because of being very thirsty.
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Those who (make oaths/solemnly promise to do something) using the names of their shameful gods of Samaria, and those who solemnly promise to do something [using the name of] the god of Dan, and those who solemnly promise to do something [using the name of] the god of Beersheba, will all die; and they will never live again.”
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

< Amos 8 >