< Amos 4 >
1 You [wealthy women] of Samaria [have grown fat like] [MET] the fat cows of the Bashan [region]. You oppress poor people and you cause needy people to suffer. And you say to your husbands, “Bring us [more wine] to drink!”
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 But Yahweh [our] God has said this: “Because I am holy, I solemnly promise this: It will [soon] be the time when you all will be taken [to another country]; [your enemies will take you away as though they are] using sharp hooks [DOU] [to grab you].
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 [Your enemies] will drag you out through breaks/holes [in your city walls], and they will throw you outside the city. [That will surely happen because I], Yahweh, have said it!
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Go to Bethel and Gilgal [towns where many people worship me] and sin more and more [SAR]! [I say that not because I want you to do it], [but because it is what you have always been doing]! Offer sacrifices on the morning [after you arrive], [and bring me] (a tithe/one tenth) of your crops the next day.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 Bring offerings of bread to thank me, and [other] offerings that are not required/commanded, and boast about [these offerings that you bring], because that is what you like to do, [but you do it to impress others, not to please me]. [That is certainly true, because I], Yahweh, have said it.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 I [am the one who] caused there to be no food in any of your cities and towns [DOU], but you rejected me in spite of that.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 When it was still three months before [the time of] harvesting [crops], [at the time when your crops needed rain the most], I prevented rain from falling. [Sometimes] I allowed rain to fall on some towns and prevented it from falling on other towns. Rain fell on some fields, but it did not fall on other fields, with the result that [the soil in] those fields [where it did not rain] dried up.
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 People would stagger from one town to another town to find water, but they could not even get enough water to drink, but in spite of that, you have not returned to me. [That is certainly true because I], Yahweh, have said it!
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 I caused your grain fields to dry up; I caused your gardens and vineyards to be struck/destroyed by (blight/hot winds) and mildew. [I sent] locusts to eat [the leaves on] your fig trees and olive trees, but in spite of that, you rejected me. [That is certainly true because I], Yahweh, have said it!
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 I caused you to experience (plagues/severe sicknesses) like the plagues [that I sent to the people] of Egypt. I caused [many of] your young men to die in battles. I allowed [your enemies] to capture your horses. [Many of your soldiers were killed, ] and I caused your camps to be filled with the smell/stink of their [decaying] corpses. But in spite of that, you rejected me. [That is certainly true, because] I, Yahweh, have said it!
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 I got rid of many of you, like I got rid of [the people in] Sodom and Gomorrah. [Those of] you who [did not die] were like [SIM] a burning stick that was snatched from a fire [so that it would not burn completely]. But in spite of that, you rejected me. [That is certainly true, because I], Yahweh, have said it!
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 So [now], you [people of] Israel, I am going to punish you. Prepare to stand in front of me, your God, [when I judge you]!
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 I created the mountains, and [I] created winds. I reveal to humans what I am thinking. I [sometimes] cause the daylight to become dark [like the night]. I [rule over everything]; I [even] walk on the highest mountains on the earth! I am the Commander of the armies of angels!”
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.