< Amos 2 >

1 Yahweh [also] said this: “[I will punish the people of] Moab because of the many sins [that they have committed]; I will not change my mind about punishing them, because they [dug up] the bones of the king of Edom and burned them completely, with the result that [the ashes became as white] as lime.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
2 So I will cause a fire to completely burn the fortresses of Kerioth [city in Moab]. [People will hear soldiers] shouting and blowing trumpets [loudly] while I am causing Moab to be destroyed
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
3 [and while] I am getting rid of its king and all its leaders. [That will surely happen because I], Yahweh, have said it!”
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Yahweh [also] said this: “[I will also punish the people of] Judah because of the many sins [that they have committed]; I will not change my mind about punishing them, because they have rejected what I taught them and they have not obeyed my commands. They have been deceived [and persuaded to worship false gods], the same [gods] that their ancestors [worshiped].
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
5 So I will cause a fire to completely burn [everything in] Judah, including the fortresses in Jerusalem.”
Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
6 Yahweh [also] said this: “[I will punish the people of] Israel because of the many sins [that they have committed]; I will not change my mind about punishing them, because they sell righteous [people] to get [a small amount of] silver; they sell poor [people, causing them to become slaves], getting for [each of] them [only the amount of money with which they could buy] a pair of sandals.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 [It is as though] they trample the poor people into the dirt and do not allow those who are helpless to be treated fairly. Men and their fathers dishonor me [MTY] by both having sex [EUP] with the same [slave] girl.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
8 [When poor people borrow money], [the lenders force those people to give to them a piece of clothing] for them to keep until he can pay back the money. [But at the end of each day, instead of returning that garment as Yahweh had commanded them to], they lie down on that garment at the places where they worship [their gods]! They fine people, and with that money [they buy] wine and drink it in the temples of their gods!
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 [Long ago, ] to assist your ancestors, I got rid of the Amor people-group. They [seemed to be] as tall as cedar [trees] and as strong as oak [trees], but I got rid of them completely, [as easily as someone cuts off] [MET] the branches of a tree and then digs out all its roots.
“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 I brought your [ancestors] out of Egypt, and [then] I led them through the desert for 40 years. And then I enabled them to conquer/possess the Amor area.
Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 I chose some of you Israelis to be prophets, and I chose others to be Nazir-men [who were completely dedicated to me]. You people of Israel certainly [RHQ] know that what I have said is true!
“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
12 But you commanded the prophets to not speak the messages that [I gave to] them, and you persuaded the Nazir-men to drink wine, [which I told them never to do].
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 So I will crush you like [SIM] [the wheels of] a wagon that is loaded with grain crushes [whatever it rolls over].
“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 [Even] if you run fast, you will not escape; [even] if you are strong, [it will be as though] you are weak, and warriors will be unable to save themselves.
Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
15 [Even] if you are able to shoot arrows [well], you will be forced to retreat [LIT]; [even] if you run fast or if you ride [away] on a horse, you will not [be able to] save yourself.
Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
16 [Even] warriors who are very brave will drop their weapons when they try to flee on the day [that I get rid of them]. [That will surely happen because I], Yahweh, have said it.”
Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.

< Amos 2 >