< 2 Samuel 6 >
1 Then David chose 30,000 Israeli men and gathered them together.
Dafidi sì tún kó gbogbo àwọn akọni ọkùnrin ní Israẹli jọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
2 He led them to the place in Judah [formerly] called Baalah, [now called Kiriath-Jearim]. They went in order to bring from there [to Jerusalem] the sacred chest, which had the name of Yahweh, the leader of the armies of [the angels in] heaven, written on it, and which had the [statues of the] winged creatures on top of it. Between those statues was where Yahweh spoke messages about ruling his people [MTY].
Dafidi sì dìde, ó sì lọ àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ́ lọ́dọ̀ rẹ́, láti Baalahi ní Juda wá, láti mú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run tí ibẹ̀ wá, èyí tí a ń pe orúkọ rẹ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó jókòó láàrín àwọn kérúbù.
3 The sacred chest was in the house of Abinadab, on top of a hill. They went there, and they put the chest on a new cart. Uzzah and Ahio, the two sons of Abinadab, were guiding [the oxen that were pulling the cart].
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà gun kẹ̀kẹ́ tuntun kan, wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu wá, èyí tí ó wà ní Gibeah: Ussa àti Ahio, àwọn ọmọ Abinadabu sì ń dá kẹ̀kẹ́ tuntun náà.
4 Uzzah walked alongside the cart, and Ahio walked in front of it.
Wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu jáde wá, tí ó wà ní Gibeah, pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, Ahio sì ń rìn níwájú àpótí ẹ̀rí náà.
5 David and all the Israeli men were celebrating in God’s presence, singing with all their strength and [playing] lyres and harps, and beating tambourines, and clashing castanets and cymbals.
Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì ṣiré níwájú Olúwa lára gbogbo onírúurú ohun èlò orin tí a fi igi arère ṣe àti lára ìlù haapu, ní ara tambori, sisitirumu àti lára kimbali.
6 But when they came to the place where Nacon threshed grain, the oxen stumbled. So Uzzah put his hand on the sacred chest to (steady it/prevent it from falling [off the cart]).
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Nakoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, ó sì dìímú, nítorí tí màlúù kọsẹ̀.
7 Yahweh immediately became very angry with Uzzah, and he killed him right there alongside the sacred chest, because he had touched the chest, [and Yahweh had commanded that only the descendants of Levi who help the priests should touch the sacred chest].
Ìbínú Olúwa sì ru sí Ussa; Ọlọ́run sì pa á níbẹ̀ nítorí ìṣísẹ̀ rẹ̀; níbẹ̀ ni ó sì kù ní ẹ̀bá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
8 David was angry because Yahweh had punished Uzzah. So ever since that time, that place has been called ‘The Punishment of Uzzah’.
Inú Dafidi sì bàjẹ́ nítorí tí Olúwa gé Ussa kúrò, ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Peresi-Usa títí ó fi di òní yìí.
9 David was [also] afraid of [what else] Yahweh [would do to punish them], so he said, “(How can I take the sacred chest with me [to Jerusalem]?/I am afraid to take the sacred chest with me [to Jerusalem].)” [RHQ]
Dafidi sì bẹ̀rù Olúwa ní ọjọ́ náà, ó sì wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò ti ṣe tọ̀ mí wá?”
10 So he did not want to take the sacred chest to Jerusalem. Instead, they took it to another place; they took it to the house of Obed-Edom, from Gath [city].
Dafidi kò sì fẹ́ mú àpótí ẹ̀rí Olúwa sọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìlú Dafidi; ṣùgbọ́n Dafidi sì mú un yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
11 They left the sacred chest in the house of Obed-Edom for three months, and [during that time] Yahweh blessed Obed-Edom and his family.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì gbé ní ilé Obedi-Edomu ará Gitti ní oṣù mẹ́ta; Olúwa sì bùkún fún Obedi-Edomu, àti gbogbo ilé rẹ̀.
12 Later, people told David, “Yahweh has blessed Obed-Edom and his family because [he is taking care] of the sacred chest!” When David heard that, he [and some other men] went to Obed-Edom’s house, and very joyfully brought the sacred chest from there to Jerusalem.
A sì rò fún Dafidi ọba pé, “Olúwa ti bùkún fún ilé Obedi-Edomu, àti gbogbo èyí tí í ṣe tirẹ̀, nítorí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.” Dafidi sì lọ, ó sì mú àpótí ẹ̀rí náà gòkè láti ilé Obedi-Edomu wá sí ìlú Dafidi pẹ̀lú ayọ̀.
13 [This time, descendants of Levi] were carrying the sacred chest, but when they had walked only six steps, they stopped, and there David killed a bull and a fat calf, and offered them to Yahweh for a sacrifice.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa bá sì ṣí ẹsẹ̀ mẹ́fà, òun a sì fi màlúù àti ẹran àbọ́pa rú ẹbọ.
14 David was wearing [only] a linen cloth wrapped around his waist, and was dancing very energetically to honor Yahweh.
Dafidi sì fi gbogbo agbára rẹ̀ jó níwájú Olúwa; Dafidi sì wọ efodu ọ̀gbọ̀.
15 David and the Israeli men took the sacred chest up [to Jerusalem], shouting [loudly] and blowing trumpets.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, pẹ̀lú ìhó ayọ̀, àti pẹ̀lú ìró ìpè.
16 While they were carrying the sacred chest into the city, [David’s wife] Michal, who was Saul’s daughter, looked out the window [of her house]. She saw King David leaping and dancing to honor Yahweh. So she was disgusted with him.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wọ ìlú Dafidi wá; Mikali ọmọbìnrin Saulu sì wo láti ojú fèrèsé, ó sì rí Dafidi ọba ń fò sókè ó sì ń jó níwájú Olúwa; òun sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
17 They brought the sacred chest into the tent that David had erected for it. Then David gave to Yahweh offerings to be completely burned [on an altar], and other offerings to maintain fellowship with Yahweh.
Wọ́n sì mú àpótí ẹ̀rí Olúwa náà wá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ sípò rẹ̀ láàrín àgọ́ náà tí Dafidi pa fún un. Dafidi sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ níwájú Olúwa.
18 When David had finished offering those sacrifices, he asked Yahweh, the Commander of the armies [of the angels], to bless the people.
Dafidi sì parí ìṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ náà, ó sì súre fún àwọn ènìyàn náà ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
19 He also distributed food to all the people. To each Israeli man and woman he gave a loaf of bread, some meat, and a raisin cake. Then all the people returned to their homes.
Ó sì pín fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, àní fún gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn Israẹli, àti ọkùnrin àti obìnrin; fún olúkúlùkù ìṣù àkàrà kan àti ekìrí ẹran kan, àti àkàrà díndín kan. Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì túká lọ, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
20 When David went home to [ask Yahweh to] bless his family, his wife Michal came out to meet him. She said to him, “Maybe you, the king of Israel, [think that you] [IRO] were honoring yourself today, but really, you acted like a fool, uncovering yourself while the female servants of your officials were watching!”
Dafidi sì yípadà láti súre fún àwọn ará ilé rẹ̀, Mikali ọmọbìnrin Saulu sì jáde láti wá pàdé Dafidi, ó sì wí pé, “Báwo ni ọba Israẹli ṣe ṣe ara rẹ̀ lógo bẹ́ẹ̀ lónìí, tí ó bọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ lónìí lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn lásán tí ń bọ́ra rẹ̀ sílẹ̀.”
21 David replied to Michal, “[I was doing that] to honor Yahweh, who chose me instead of your father and other members of his family, to be the king of the Israeli people, the people who belong to Yahweh. And I will [continue to] dance to honor Yahweh!
Dafidi sì wí fún Mikali pé, “Níwájú Olúwa ni, ẹni tí ó yàn mí fẹ́ ju baba rẹ lọ, àti ju gbogbo ìdílé rẹ lọ, láti fi èmi ṣe olórí àwọn ènìyàn Olúwa, àní lórí Israẹli, èmi ó sì súre níwájú Olúwa.
22 [Even though you think that what I did] was disgraceful, I will continue to do it even more. You may despise me [because of what I did], but the women whom you were talking about will honor me!”
Èmi ó sì tún rẹ ara mi sílẹ̀ jú bẹ́ẹ̀ lọ, èmi ó sì ṣe aláìníyìn lójú ara mi, àti lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà ti ìwọ wí, lọ́dọ̀ wọn náà ni èmi ó sì ní ògo.”
23 [As a result, ] Saul’s daughter Michal never gave birth to any children.
Mikali ọmọbìnrin Saulu kò sì bí ọmọ, títí o fi di ọjọ́ ikú rẹ̀ nítorí tí ó sọ̀rọ̀-òdì yìí sí Dafidi.