< 2 Samuel 13 >

1 David’s son Absalom had a beautiful sister named Tamar. Another of David’s sons, Amnon, was attracted to Tamar.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
2 He wanted [to have sex with] [EUP] his half-sister very much, with the result that he made himself sick [thinking about her all the time]. But it was not possible for Amnon to get her, because she was a virgin, [so they kept men away from her].
Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
3 But Amnon had a friend named Jonadab, who was the son of David’s brother Shimeah. Jonadab was a very crafty/shrewd man.
Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
4 [One day] Jonadab said to Amnon, “You are the king’s son, but every day I see that [RHQ] you seem very depressed/sad. What is your problem?” Amnon replied, “I (am in love/want to sleep) [EUP] with Tamar, my half-brother Absalom’s sister.”
Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
5 Jonadab said to him, “Lie down on your bed, and pretend that you are sick. When your father comes to see you, say to him, ‘Allow my half-sister Tamar to come and give me some food to eat. She can prepare the food while I am watching her. Then she can serve it to me herself.’”
Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
6 So Amnon lay down, and pretended that he was sick. When the king came to see him, Amnon said to him, “[I am sick; ] please allow my half-sister Tamar to come and make a couple scones/dumplings for me while I am watching, and then she can serve them to me.”
Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
7 So David sent a message to Tamar in the palace, saying “Amnon [is sick and he wants you to] go to his house and prepare some food for him.”
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
8 So Tamar went to Amnon’s house, where he was lying in bed. She took some dough and kneaded it, and formed it into some scones/dumplings while he was watching her. Then she baked them.
Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
9 She took them out of the pan and put them [on a plate] in front of him, but he refused to eat them. Then he said to everyone else in the room, “All the rest of you, leave me now!” So all the others left his [room].
Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
10 Then Amnon said to Tamar, “Bring the food into my room and serve it to me.” So Tamar took into his room the scones/dumplings that she had made.
Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
11 But when she brought them close for him to eat them, he grabbed her and said to her, “Come to bed with me!”
Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
12 She replied, “No, do not force me to do such a disgraceful thing! We never do things like that in Israel! That would be awful/terrible!
Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
13 As for me, if I did that, I would not be able to [RHQ] endure being disgraced by having done that. And as for you, everyone in Israel would condemn you for having done such a disgraceful deed. So I plead with you, talk to the king. I am sure that he will allow me to marry you.”
Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
14 But he would not listen to her. He was stronger than she was, so he forced her to have sex with him.
Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
15 Then Amnon hated her very much. He hated her much more than he had desired her. He said to her, “Get up and get out of here!”
Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
16 But she said to him, “No! It would be very wrong for you to send me away. It would be worse than what you just did to me!” But he would not listen to her.
Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
17 He summoned his personal servant and said to him, “Take this woman outside, away from me, and lock the door [so that she cannot come in again]!”
Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
18 So the servant put her outside and locked the door. Tamar was wearing a long robe with long sleeves, which was the clothing that was usually worn by the unmarried daughters of the king at that time.
Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
19 But Tamar tore the long robe that she was wearing, and put ashes on her head [to show that she was very sad]. Then she put her hands on her head [to show that she was grieving], and she went away, crying.
Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
20 Her brother Absalom [saw her and] said to her, “Has your half-brother Amnon [DOU] forced you to have sex with him [EUP]? Please, my sister, do not tell anyone, and do not become depressed/sad.” So Tamar went to live in Absalom’s house, and she was very sad and lonely.
Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
21 When King David heard about all that, he became very angry.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
22 And Absalom hated Amnon, because he had raped his sister, so he would not speak to Amnon about anything.
Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
23 Two years later, Absalom’s servants were shearing sheep at Baal-Hazor, which is near [a town named] Ephraim. [When they finished shearing the sheep, they celebrated], and Absalom invited all the king’s sons [to come and celebrate].
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
24 Absalom went to the king and said to him, “Sir, my servants have been shearing my sheep. Please come with your officials [to celebrate] with us!”
Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
25 But the king replied, “No, my son, it would not be good for all of us to go, because it would cause you to do a lot of work and spend a lot of money for food.” Absalom continued urging him, but the king would not go. Instead, he said that he hoped/desired that God would bless them [while they celebrated].
Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
26 Then Absalom said, “If you will not go, please allow my half-brother Amnon to go with us.” But the king replied, “Why [do you want] him to go with you?”
Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
27 But Absalom continued to insist, so finally the king permitted Amnon and all David’s other sons to go with Absalom.
Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
28 [So they all went. And at the celebration], Absalom commanded his servants, “Notice when Amnon has become a bit drunk from the wine. Then when I signal to you, kill him. Do not be afraid; you will be doing this [only] because I told you [RHQ] to do it. So be courageous and do it!”
Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
29 So Absalom’s servants did what Absalom told them to do. [They killed Amnon]. All the rest of David’s sons [saw what happened and] fled, riding on their mules.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
30 While they were on their way home, someone [went quickly and] reported to David, “Absalom has killed all of your other sons; none of them is still alive!”
Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
31 The king stood up, tore his clothes [because he was extremely sad], and then he threw himself down on the ground. All the servants who were there also tore their clothes.
Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
32 But Jonadab, the son of David’s brother Shimeah, said, “Your Majesty, [I am sure that] they have not killed all your sons. [I am sure that] only Amnon is dead, because Absalom has determined to do this ever since the day that Amnon raped [EUP] his half-sister Tamar.
Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
33 So, your majesty, do not believe the report that all your sons are dead. [I am sure that] only Amnon is dead.”
Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
34 In the meantime, Absalom ran away. Just then, the soldier/sentry [who was standing on the city wall] saw a large crowd of people coming down the hill along the road from Horonaim. [He ran and told the king what he had seen].
Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
35 Jonadab said to the king, “Aha! What I told you is true. Your other sons [are alive and] have come!”
Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
36 And as soon as he said that, David’s sons came in. They all started crying, and David and all his officials also cried very much.
Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
37 But Absalom had fled. He went to stay with the king of [the] Geshur [region], who was Talmai the son of Ammihud. Absalom stayed there for three years. David mourned for his son Amnon for a long time,
Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
39 but after that, he desired very much to see Absalom, because he was no longer grieving about Amnon being dead.
Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.

< 2 Samuel 13 >