< 2 Samuel 12 >

1 Yahweh [told the prophet Nathan what David had done, and he] sent Nathan to tell [this story to] David: “[I heard about] two men [who] were living in a certain city. One was rich and the other was poor.
Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
2 The rich man owned a lot of cattle and sheep.
Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 But the poor man had only one little female lamb, which he had bought. He raised the lamb, and it grew up with his children. He would give the lamb some of his own food and let it drink from his cup. He let the lamb sleep in his arms. The lamb was like a daughter to him.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
4 [One day] a visitor came to [visit] the rich man. The rich man did not want to take one of his own animals [and kill it] to prepare a meal for the visitor. So instead, he stole the poor man’s lamb [and killed it] and prepared a meal for his visitor.”
“Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
5 [When] David [heard that, he] was very angry about [what] the rich man [had done]. He said to Nathan, “I solemnly declare that the man who did that should be executed!
Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
6 But before he is executed, he should pay back to the poor man four lambs for doing this, and for not having pity [on the poor man].”
Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
7 Nathan said to David, “You are the man [I have been talking about]! And this is what Yahweh, the God we Israelis [worship], says to you: ‘I appointed you to be king of Israel, after having rescued you from Saul.
Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
8 I gave you his palace and his wives. I caused you to become the king to rule Israel and Judah. If [you had told me that] you were not content with what I gave you, I would have given you twice as much!
Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
9 So why have you despised my commandment [about not committing adultery]? You have done what I consider to be very evil! You have arranged for Uriah to be killed in a battle by the Ammon people-group’s soldiers, and you have taken his wife to be your wife!
Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
10 You have despised me, and have taken Uriah’s wife to be your wife. So for many generations some of your descendants will die violently. [MTY, PRS]
Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
11 I solemnly declare to you that I will cause someone from your own family to bring trouble to you. I will take your wives and give them to him, and he will have sexual relations with them in the daytime, where everyone can see it, and you will know all about it.
“Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
12 What you did, you did secretly, but what I will cause to happen, everyone in Israel will be able to see it [or know about it]. [IDM]’”
Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
13 David replied, “I have sinned against Yahweh.” Nathan said to David, “Yahweh has forgiven you for your sin: You will not die [because of this sin].
Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
14 But, you have shown contempt for Yahweh by doing this. So, your baby will die.”
Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
15 Then Nathan went home. Then Yahweh caused the baby t o become very sick, the one that Uriah’s wife had given birth to.
Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
16 So David prayed to God that the child [would not die]. He (fasted/abstained from food), and he went into [the room where he slept] and lay all night on the floor.
Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
17 [The next morning] his advisors stood around him and urged him to get up. But he would not get up, and he would not eat any food with them.
Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
18 One week later the baby died. David’s servants were afraid to tell that to David. They said [to each other], “Hey, while the baby was still alive, we talked to him, but he would not answer us. Now, if we tell him that the baby is dead [RHQ], he may do something to harm himself!”
Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
19 But when David saw that his servants were whispering something to each other, he realized that the baby must be dead. So he asked them, “Is the baby dead?” They replied, “Yes, he is dead.”
Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
20 Then David got up from the floor. He bathed himself, put lotions on his body, and put on other clothes, Then he went into Yahweh’s Sacred Tent and worshiped Yahweh. Then he went home. He asked his servants for some food. They gave him some, and he ate it.
Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
21 Then his servants said to him, “We do not understand [RHQ] why you have done this! While the baby was still alive, you cried for him and refused to eat anything. But now that the baby has died, [you are not crying any more!] You got up and ate some food!”
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
22 David replied, “While the baby was still alive, I fasted and cried. I thought, ‘Who knows? Yahweh may be merciful to me and not allow the baby to die’.
Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
23 But now the baby is dead. So (there is no reason for me to (fast/abstain from eating food) any more./why should I (fast/abstain from eating food) any more?) [RHQ] (Can I bring him back to me?/I certainly cannot bring him back to me!) [RHQ] [Some day] I will go to where he is, but he will not return to me.”
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
24 Then David comforted his wife, Bathsheba. Then he (slept/had sexual relations) with her, and she [became pregnant again and] gave birth to another son. David named that son Solomon. Yahweh loved that little boy.
Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
25 He told the prophet Nathan to tell David to name the baby boy Jedediah [which means ‘loved by Yahweh’, ] because Yahweh loved him.
Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
26 (Meanwhile/While all that was happening), Joab’s [soldiers] attacked Rabbah, [the capital city] of the Ammon people-group; and they captured the king’s fortress.
Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
27 Then Joab sent messengers to David, to tell him this: “My troops are attacking Rabbah, and we have captured the city’s water supply.
Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
28 Now gather your troops and come and surround the city and capture it. If you do not do that, my troops will capture the city and it will then be named ‘the City of Joab’.”
Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
29 So David gathered all his troops. They went [with David] to Rabbah and attacked it and captured it.
Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
30 Then David took the crown from the head of the king of Rabbah (OR, from the head of [Milcom] the god of Rabbah) and put it on his own head. It [was very heavy; it] weighed (75 pounds/34 kg.), and it had many very valuable stones fastened to it. His soldiers also took many other valuable things from the city.
Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
31 Then they brought the people of Rabbah out of the city and forced them to [work for them] using saws and iron picks and axes. David’s troops also forced them to make bricks. David’s soldiers did this in all the towns of the Ammon people-group. Then David and all of his army returned to Jerusalem.
Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.

< 2 Samuel 12 >