< 2 Kings 19 >
1 When King Hezekiah heard what they reported, he tore his clothes and put on clothes made of rough cloth [because he was very distressed]. Then he went to the temple [to ask God what to do].
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
2 He summoned Eliakim and Shebna and the (older/most important) priests, who were also wearing clothes made of rough sackcloth, and told them to talk to me.
Ó sì rán Eliakimu olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 He said to them, “Tell this to Isaiah: ‘King Hezekiah says that we are having great distress/trouble now. [Other nations are causing] us to be insulted and disgraced. We are like [MET] a woman who is about to give birth to a child, but she does not have the strength that she needs to do it.
Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Hesekiah sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.
4 Perhaps Yahweh your God has heard everything that the official from Assyria said. Perhaps he knows that his boss/master, the king of Assyria, sent him to insult the all-powerful God, and that Yahweh will rebuke/punish him for what he said.’ And he requests that you pray for the few of us who are still alive [here in Jerusalem].”
Ó lè jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yóò gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ olùdarí pápá, ẹni tí ọ̀gá rẹ̀, ọba Asiria, ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣẹ̀sín, yóò sì bá a wí fún ọ̀rọ̀ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún ìyókù àwọn tí ó wà láààyè.”
5 When the messengers from Hezekiah came to Isaiah,
Nígbà tí ìránṣẹ́ ọba Hesekiah lọ sí ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 Isaiah said to them, “[Go back to] your boss/master [and] tell him, ‘This is what Yahweh says: Those messengers from the king of Assyria have said evil things about me. But you should not be disturbed because of what they said.
Isaiah wí fún wọn pé, “Sọ fún ọ̀gá rẹ, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa sọ pé: Ẹ má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ̀yin ti gbọ́—àwọn ọ̀rọ̀ ìhàlẹ̀ pẹ̀lú èyí ti ọba Asiria ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Listen to this: I will cause Sennacherib to hear a rumor that will worry him, [that a foreign army is about to attack his country]. So he will return to his own country, and there I will cause him to be assassinated by [men using] swords.’”
Gbọ́! Èmi yóò rán ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ nígbà tí ó bá sì gbọ́ ariwo, yóò sì padà sí ìlú rẹ̀, níbẹ̀ ni èmi yóò sì gbé gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 The official from Assyria found out that the King of Assyria [and his army] had left Lachish [city], and that they were attacking Libnah, [which is a nearby city]. So the official went there [to report to him what had happened in Jerusalem].
Nígbà tí olùdarí pápá gbọ́ wí pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi ó sì padà ó sì rí ọba níbi ti ó gbé ń bá Libina jà.
9 Soon after that, King Sennacherib received a report that King Tirhakah of Ethiopia was leading his army, and was coming to attack them. So before King Sennacherib left Libnah [to fight against the army from Ethiopia], he sent other messengers to King Hezekiah with a letter.
Nísinsin yìí, Sennakeribu sì gbọ́ ìròyìn wí pé Tirakah, ọba Etiopia ti Ejibiti wá ó sì ń yan jáde lọ láti lọ bá a jagun. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tún rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ yìí pé,
10 [In the letter] he wrote this to Hezekiah: “Do not allow your god on whom you are relying to deceive you by promising that [the city of] Jerusalem will not be captured by my army [MTY].
“Sọ fún Hesekiah ọba Juda pé, má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé kí ó tàn ó jẹ nígbà tí ó wí pé, ‘Jerusalẹmu a kò ní fi lé ọwọ́ ọba Asiria.’
11 You have certainly heard what the armies of the kings of Assyria have done to all the other countries. Our armies have completely destroyed them. So, (do you think that you will escape?/do not think that your god will save you!) [RHQ]
Lóòótọ́ ìwọ ti gbọ́ gbogbo ohun tí ọba Asiria tí ó ṣe sí gbogbo àwọn ìlú, ó pa wọ́n run pátápátá. Ìwọ yóò sì gbàlà?
12 Did the gods of the nations that were about to be destroyed by the armies of the previous kings of Assyria rescue them? Did those gods rescue the people in the Gozan region and in Haran and Rezeph [cities in northern Syria] and the people of Eden who had been (deported/forced to go) to Tel-Assar [city]? None of the gods of those cities were able to rescue them.
Ṣé àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè tí a ti parun láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá mi gbà wọ́n là: òrìṣà Gosani, Harani Reṣefu àti gbogbo ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 What happened to the kings of Hamath and Arpad and Sepharvaim and Ivvah [cities] [RHQ]? [Most of them are dead, and the other people were deported]!”
Níbo ni ọba Hamati wa, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi, ti Hena, tàbí ti Iffa gbé wà?”
14 Hezekiah took the letter that the messengers gave him, and he read it. Then he went up to the temple and spread out the letter in front of Yahweh.
Hesekiah gba lẹ́tà láti ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ ó sì kà á. Nígbà náà ó sì lọ sí òkè ilé tí a kọ́ fún Olúwa ó sì tẹ́ ẹ síwájú Olúwa.
15 Then Hezekiah prayed, “Yahweh, the God whom to whom we Israelis belong, you are seated on your throne above the [statues of] creatures with wings, [above the Sacred Chest]. Only you are truly God. You rule all the kingdoms on this earth. You are the one who created [everything on] the earth and [in] the sky.
Hesekiah gbàdúrà sí Olúwa: “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ń gbé ní àárín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí gbogbo ìjọba tí ó wà láyé, ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
16 So, Yahweh, please listen to what I am saying, and look [at what is happening]. And listen to what King Sennacherib has said to insult you, the all-powerful God.
Dẹtí sílẹ̀, Olúwa kí o sì gbọ́; la ojú rẹ, Olúwa, kí o sì rí i, gbọ́ ọ̀rọ̀ Sennakeribu tí ó rán láti fi bú Ọlọ́run alààyè.
17 “Yahweh, it is true that [the armies of] the kings of Assyria have completely destroyed many nations, and ruined their land.
“Òtítọ́ ni, Olúwa, wí pé ọba Asiria ti pa orílẹ̀-èdè wọ̀nyí run àti ilẹ̀ wọn.
18 And they have thrown the idols of those nations into fires and burned them. But [that was not difficult to do, because] they were not gods. They were only statues made of wood and stone, idols that were shaped by humans, [and that is why they were destroyed easily].
Wọ́n ti ju òrìṣà wọn sínú iná wọn sì ti bà wọ́n jẹ́, nítorí pé wọn kì í ṣe ọlọ́run. Ṣùgbọ́n, wọ́n jẹ́ igi àti òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ ènìyàn.
19 So now, Yahweh our God, please rescue us from the power [MTY] [of the king of Assyria], in order that the people in all the kingdoms of the world will know that you, Yahweh, are the only one who is truly God.”
Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run wa, gbà wá kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ìjọba lórí ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé ìwọ nìkan ṣoṣo ni, Olúwa Ọlọ́run wa.”
20 Then Isaiah sent this message to Hezekiah: “This is what Yahweh, the God to whom we Israelis belong, says: 'I have heard what you prayed to me about Sennacherib, the king of Assyria.
Nígbà náà Isaiah ọmọ Amosi rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Sennakeribu ọba Asiria.
21 This is what I say to him: “The people of Jerusalem [MTY] despise you and make fun of you. They wag/shake their heads to mock you while you flee from here.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, “‘Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni kẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu mi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.
22 Who do you think that you are despising and ridiculing? Who do you think you were shouting at? Who do you think you were looking at very proudly/arrogantly? It was I, the holy God whom the Israelis worship.
Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀? Lórí ta ni ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga? Lórí ẹni mímọ́ ti Israẹli!
23 The messengers that you sent made fun of me. You said, 'With my many chariots I have gone to the highest mountains, even to the highest mountains in Lebanon. We have cut down its tallest cedar trees and its nicest pine/cyprus trees. We have been to the most distant/remote peaks and to its dense forests.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, “Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi a sì lọ sí orí òkè ìbùwọ̀ rẹ̀ sínú ibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ̀.
24 We have dug wells in other countries and drank water from them. And by marching through [MTY] the streams of Egypt, we dried them all up [HYP]!”’
Mo ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì, mo sì mu omi níbẹ̀. Pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi, èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Ejibiti.”
25 [‘But I reply], “Have you never heard that long ago I determined [that those things would happen]? I planned it long ago, and now I have been causing it to happen. I planned that your army would have [the power to] capture many cities that were surrounded by high walls, and cause them to become piles of rubble.
“‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́? Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án. Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀; nísinsin yìí mo ti mú wá sí ìkọjá pé ìwọ ti yí ìlú olódi padà dí òkìtì àlàpà òkúta.
26 The people who lived in those cities have no power, and as a result they became dismayed and discouraged. They are as frail as plants and grass in the fields, as frail as grass that grows on the roofs of houses and is scorched by the hot east wind.
Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa, wọ́n ti dà á láàmú wọ́n sì ti ṣọ́ di ìtìjú. Wọ́n dàbí koríko igbó lórí pápá, gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbàsókè, gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.
27 “But I know [everything about you]. I know when you are in your house and when you go outside; I also know that you are (raging/speaking very angrily) against me.
“‘Ṣùgbọ́n èmi mọ ibi tí ìwọ dúró àti ìgbà tí ìwọ bá dé tàbí lọ àti bí ìwọ ṣe ìkáàánú rẹ: sí mi.
28 So, because you have raged against me, and because I have heard [MTY] you speak very proudly/arrogantly, [it will be as though] I will put a hook in your nose and an iron (bit/piece of metal) in your mouth [in order that I can lead you where I want you to go], and I will force you to return [to your own country] on the same road on which you came here, [without conquering Jerusalem].” '
Ṣùgbọ́n ìkáàánú rẹ sí mi àti ìrora rẹ dé etí mi, Èmi yóò gbé ìwọ̀ mi sí imú rẹ àti ìjánu mi sí ẹnu rẹ, èmi yóò mú ọ padà nípa wíwá rẹ.’
29 Then Isaiah said to Hezekiah, “This is what will happen to prove [that I am telling the truth]: This year and next year you [and your people] will be able to harvest only (wild grain/grain that grows without having been planted). But the following year, you [Israelis] will be able to plant grain and harvest it, and to plant vineyards and eat the grapes that you harvest.
“Èyí yóò jẹ́ àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ọdún yìí ìwọ yóò jẹ ohun tí ó bá hù fún rara rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó bá hù jáde láti inú ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, gbìn kí o sì kórè, gbin ọgbà àjàrà kí o sì jẹ èso rẹ̀.
30 The people [MTY] in Judah who remain alive will prosper and have many children; they will be like plants whose roots go deep down into the ground and which produce much [MET].
Lẹ́ẹ̀kan sí i ìyókù ti ilé Juda yóò sì tún hu gbòǹgbò lábẹ́, yóò sì so èso lókè.
31 There will be many people in Jerusalem [DOU] who will survive, because Yahweh, the commander of the armies of angels in heaven, wants [PRS] it to happen.
Láti inú Jerusalẹmu ní àwọn ìyókù yóò ti wá àti láti orí òkè Sioni ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó sá àsálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ṣe èyí.
32 So this is what Yahweh, says about the king of Assyria: ‘His armies will not enter this city; they will not even shoot any arrows into it! His soldiers will not march outside the city gates carrying shields, and they will not even build high mounds of dirt against [the city walls] [to enable them to attack the city].
“Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa ti ọba Asiria: “Kò ní wọ ìlú yìí tàbí ta ọfà síbí. Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lú àpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
33 Their king will return to his own country on the same road on which he came here. He will not enter this city! [That will happen because] I, Yahweh have said it!
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá ni yóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí, ni Olúwa wí.
34 I will defend this city and prevent it from being destroyed. I will do this for the sake of my own reputation and because of what I promised to King David, who served me well.'”
Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí, èmi yóò sì pa á mọ́ fún èmi tìkára mi àti fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.”
35 That night, an angel from Yahweh went out to where the army of Assyria had put up their tents, and killed 185,000 of their soldiers! When the rest of their soldiers woke up the next morning, they saw that there were corpses everywhere!
Ní alẹ́ ọjọ́ náà, angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Asiria. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
36 Then King Sennacherib left and went home to Nineveh, [the capital of Assyria].
Bẹ́ẹ̀ ni Sennakeribu ọba Asiria wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Ninefe ó sì dúró níbẹ̀.
37 One day, when he was worshiping in the temple of his god Nisroch, two of his sons, Adrammelech and Sharezer, killed him with their swords. Then they escaped and went to [the] Ararat [region, northwest of Nineveh]. And another of Sennacherib's sons, Esarhaddon, became the king of Assyria.
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nisroki, ọmọkùnrin rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati Esarhadoni ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.