< 1 Samuel 20 >

1 David ran away from [the] Naioth [section] of Ramah [city]. He went to Jonathan and asked him, “What have I done [to displease your father]? What did I do that was wrong? Why is he trying to kill me?”
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Jonathan replied, “My father is surely not trying to kill you! He always tells me before he does anything that he is planning. He tells me about important things and unimportant things that he plans to do. (Why would he refuse to tell me [if he were planning to kill me]?/I am sure that he would not refuse to tell me [if he were planning to kill you].) [RHQ] So what you are saying cannot be true.”
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 Then David solemnly declared this to Jonathan: “Your father knows very well that you and I are very good friends, so he says to himself, ‘I will not tell Jonathan [what I am going to do]. If I tell Jonathan, he will be upset/distressed, [and then he will tell David].’ But just as certain as Yahweh lives and you live, I am only one step away from being killed.”
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 Jonathan said to David, “I will do whatever you tell me to do.”
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 David replied, “Tomorrow we will celebrate the Festival of the New Moon. I always eat with the king at that festival. But tomorrow I will hide in the field, and I will stay there for one night. I will stay there until the evening of the day after tomorrow.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 If your father asks why I am not there at the festival, say to him, ‘David requested me to allow him to go to his home in Bethlehem, where his family will offer the sacrifice that they offer [during this festival] every year.’
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 If your father says ‘That is okay’, then I know I will be safe. But if he becomes extremely angry, you will know that he is determined to harm me.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 Please be kind to me. Yahweh heard you when you made a solemn agreement with me [that you and I will always be loyal friends]. If I deserve to be punished [MTY], kill me yourself. I do not want [RHQ] you to allow your father to punish [IDM] me.”
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 Jonathan replied, “I will never do that! But if I find out that my father is determined to harm/kill you, I will certainly warn you.” [RHQ]
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 David asked him, “How will I find out if your father answers you harshly?”
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Jonathan replied, “Come with me. We will go out into the field.” So they went together out into the field.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 There Jonathan said to David, “I promise this while Yahweh, the God whom we Israelis [worship], is listening: At this time the day after tomorrow, I will find out what my father [is thinking about you]. If he is saying good things about you, I will certainly send a message to you to tell that to you [RHQ].
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 But if he is planning to hurt/kill you, I will enable you to know [IDM] that, and enable you to go away safely. I desire that Yahweh will punish me severely if I do not do that [for you]. I desire/hope that Yahweh will be with you [and help you] like he has helped my father.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 But while I am still alive, please be kind to me in the same way that Yahweh is kind to me, and do not kill me [when you become king].
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 But [if I die, ] never stop being kind to my family, [even] after Yahweh has gotten rid of all your enemies all over the earth.”
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 [David agreed]. So Jonathan made a solemn agreement with David. And he said, “I hope/desire that Yahweh will get rid of all your enemies.”
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 And Jonathan requested David to repeat his solemn promise to be his close friend, because Jonathan loved David as much as he loved himself.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 Then Jonathan said, “Tomorrow we will celebrate the Festival of the New Moon. When you are not sitting at your place when we eat, my father will (miss you/see that you are not there).
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 The day after tomorrow, in the evening, go to the place where you hid before. Wait by the pile of stones.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 I will come out and shoot three arrows as though I were trying to shoot at a target. [The arrows will hit the ground] close to the pile of stones.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 Then I will send a boy to bring the arrows back to me. If you hear me say to him, ‘They are closer to me’, then as surely as Yahweh lives, you will know that everything is fine, [and that Saul will not kill you].
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 But if I tell him, ‘The arrows are farther away’, you will know that you must leave immediately, because Yahweh wants you to run away.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 I hope/desire that Yahweh will watch you and me and enable us to never forget what we have promised each other.”
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 So David went and hid in the field. When the Festival of the New Moon started, the king sat down to eat.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 He sat where he usually sat, close to the wall. Jonathan sat across from him, and Abner [the army commander] sat next to Saul. But no one was sitting in the place where David [usually sat].
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 On that day, Saul did not say anything about David, because he was thinking, “Something must have happened that caused David to become unacceptable [to worship God].”
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 But the next day, when David was not sitting at the place where he usually sat, Saul asked Jonathan, “Why has that son of Jesse not been here to eat with us yesterday and today?”
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Jonathan replied, “David earnestly requested me that I permit him to go to Bethlehem.
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 He said, ‘Please allow me to go, because our family is going to offer a sacrifice. My [older] brother insisted that I be there. So please allow me to go to be with my [older] brothers.’ [I allowed David to go], and that is the reason that he is not here eating with you.”
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 Saul was (furious/very angry) with Jonathan. He yelled at him, “You stupid bastard [EUP]! I know that you are being loyal to that son of Jesse. By doing that, you will bring shame to yourself and to your mother.
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 As long as Jesse’s son is living, you will never become the king, and you will never rule over a kingdom! So now, summon David, and bring him to me. He must be executed!”
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Jonathan asked his father, “Why should David be executed? What wrong has he done?”
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 Then Saul threw his spear at Jonathan in order to kill him, [but the spear did not hit him]. So Jonathan knew that his father really wanted to kill David.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 Jonathan was very angry, and he left the room. On that second day of the festival, he refused to eat anything. He was disgusted about what his father had done, and he was worried about David.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 The following morning Jonathan went out to the field to give a message to David, like he had agreed that he would do. He took a young boy with him.
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 Jonathan said to the boy, “Run and find the arrows that I shoot.” The boy started running, and Jonathan shot an arrow ahead of the boy.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 When the boy ran to the place where the arrow hit the ground, Jonathan called out, “The arrow is further away!” [RHQ]
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 Then he shouted to the boy, “Act quickly; do not wait! Do not stop!” The boy picked up the arrow and brought it back to Jonathan.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 But the boy did not understand the meaning of what Jonathan had said; only Jonathan and David knew.
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 Then Jonathan gave his bow and arrows to the boy and told him, “Go back to the town.”
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 When the boy left, David came out from the south side of the pile of stones behind which he had been hiding. He went to Jonathan and bowed [in front of Jonathan] three times, with his face touching the ground. Then David and Jonathan kissed each other [on the cheek/neck], and they cried together. But David cried more than Jonathan.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 Jonathan said to David, “May things go well for you as you go. Yahweh has heard what we solemnly promised to always do for each other, and what we said that our descendants must do for each other.” Then David left, and Jonathan went back to the town.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< 1 Samuel 20 >