< 1 John 3 >

1 [Think about] how much our [heavenly] Father loves us! He allows us to (say that we are/be called) his children! [And it is indeed true that] we are [his children. But people in] the world [MTY] [who are unbelievers] have not understood [who] God [is]. So they do not understand [who we are], that we [belong to God].
Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba fi fẹ́ wa, tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run; bẹ́ẹ̀ ni a sá à jẹ́. Nítorí èyí ni ayé kò ṣe mọ̀ wá, nítorí tí kò mọ̀ ọ́n.
2 Dear friends, even though (at present/now) we are God’s children, [he] has not yet (made clear/revealed) [to us] what we will be like [in the future]. However, we know that when [Christ] comes back again, we will be like him, because we will see what he is [really] like.
Olùfẹ́, ọmọ Ọlọ́run ni àwa ń ṣe nísinsin yìí, a kò ì tí i fihàn bí àwa ó ti rí: àwa mọ̀ pé, nígbà tí òun ba farahàn, àwa yóò dàbí rẹ̀; nítorí àwa yóò rí i, àní bí òun tí rí.
3 [So], all those who confidently expect [to see Christ as he actually is/what Christ is like when he returns] must keep themselves pure in every way, just like Christ, who is pure in every way.
Olúkúlùkù ẹni tí ó ba sì ní ìrètí yìí nínú rẹ̀, ń wẹ ara rẹ̀ mọ́, àní bí òun ti mọ́.
4 But everyone who continues sinning is refusing to obey [God’s] laws, because that is what sin is, refusing to obey [God’s] laws.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ó ń rú òfin pẹ̀lú, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ni rírú òfin.
5 You know that Christ came in order to completely remove [the guilt of] our sins. You know also that he never sinned.
Ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òun farahàn láti mu ẹ̀ṣẹ̀ kúrò; ẹ̀ṣẹ̀ kò sì ṣí nínú rẹ̀.
6 Those who continue [doing what] Christ wants them to, do not continue sinning repeatedly. But those who repeatedly sin have not understood [who Christ is], nor have they had a close relationship with him.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba ń gbé inú rẹ̀ kì í dẹ́ṣẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ń dẹ́ṣẹ̀ kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni kò mọ̀ ọ́n.
7 [So I urge you, ] who are all very dear to me, do not let anyone deceive you [by telling you that it is all right to sin]. If you continue doing what is right, you are righteous, just like Christ is righteous.
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín, ẹni tí ó bá ń ṣe òdodo, ó jásí olódodo, gẹ́gẹ́ bí òun tí jẹ olódodo.
8 [But] if anyone continues sinning, he is like the devil, because the devil has always been sinning. [And] the reason why God’s Son became a human being was to destroy what the devil has done.
Ẹni tí ó ba ń dẹ́ṣẹ̀ tí èṣù ni; nítorí láti àtètèkọ́ṣe ni èṣù ti ń dẹ́ṣẹ̀. Nítorí èyí ni Ọmọ Ọlọ́run ṣe farahàn, kí ó lè pa iṣẹ́ èṣù run.
9 People do not continue sinning repeatedly if they have become children of God. Instead, [they] continue [to conduct their lives according to the character/nature that God produced in them] [MET]. They cannot continually sin because God has caused them to become his children.
Ẹnikẹ́ni tí a ti ipa Ọlọ́run bí, kì í dẹ́ṣẹ̀; nítorí tí irú rẹ̀ ń gbé inú rẹ̀, kò sì lè dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé a ti ti ipa Ọlọ́run bí i.
10 Those who are God’s children are clearly different from those who are (the devil’s/Satan’s) children. [The way that we can know who are Satan’s children is this]: Those who do not do what is right are not God’s children. [Specifically], those who do not love their fellow believers are not [God’s children Instead, they are Satan’s children].
Nínú èyí ni àwọn ọmọ Ọlọ́run ń farahàn, àti àwọn ọmọ èṣù; ẹnikẹ́ni tí kò ba ń ṣe òdodo, àti ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ kì í ṣe ti Ọlọ́run.
11 The message that you heard when you first [MTY] [believed in Christ] is that we should love each other.
Nítorí èyí ni iṣẹ́ tí ẹ̀yin tí gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé ki àwa fẹ́ràn ara wa.
12 [We should] not [hate others] as did [Adam’s son], Cain, who belonged to [Satan], the evil one. [Because Cain hated his younger brother], he murdered him. (I will tell you about why he murdered his brother./Do you know why he murdered his brother [RHQ]?) It was because Cain habitually conducted his life in an evil way, and [he hated his younger brother] because his [younger] brother [conducted his life] righteously.
Kì í ṣe bí Kaini, tí í ṣe ẹni búburú, tí o sì pa arákùnrin rẹ̀. Nítorí kín ni ó sì ṣe pa á? Nítorí tí iṣẹ́ tirẹ̀ jẹ́ búburú ṣùgbọ́n tí arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ òdodo.
13 You should not be amazed/surprised, my fellow believers, when [unbelievers] [MTY] hate you.
Kì ẹnu má ṣe yà yín, ẹ̀yin ará mi, bí ayé bá kórìíra yín.
14 We know that we have been changed from [being spiritually] dead [MET] to [being spiritually] alive. We know this because we love our fellow believers. [Those who] do not love [their fellow believers] are still [spiritually] [MET] dead.
Àwa mọ̀ pé àwa tí rékọjá láti inú ikú sínú ìyè, nítorí tí àwa fẹ́ràn àwọn ará. Ẹni tí kò ba ni ìfẹ́, ó ń gbé inú ikú.
15 Those who hate [any of] their fellow believers, [God considers] [MET] them [to be] murderers. And you know that no murderer has eternal life. (aiōnios g166)
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kórìíra arákùnrin rẹ̀ apànìyàn ni, ẹ̀yin sì mọ́ pé kò sí apànìyàn tí ó ni ìyè àìnípẹ̀kun láti máa gbé inú rẹ̀. (aiōnios g166)
16 The way that we now know [how to truly] love [our fellow believers is by remembering] that Christ (voluntarily died/gave his life) for us. So, [when our fellow believers need something, we should be willing to help them. We should even be willing to] die for them.
Nípa èyí ni àwa mọ ìfẹ́ nítorí tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún wa, ó sì yẹ kí àwa fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún àwọn ará.
17 Many [of us] have the things that are necessary for us to live in this world. If we become aware that any of our fellow believers do not have what they need and [if we] refuse to ([provide for them/give to them what they need]), it is clear that we do not love God [as we claim/say that we do].
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ni ohun ìní ayé, tí ó sì ri arákùnrin rẹ̀ tí ó ṣe aláìní, tí ó sì sé ìlẹ̀kùn ìyọ́nú rẹ̀ mọ́ ọn, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe ń gbé inú rẹ̀?
18 [I say to] all of you whom I love dearly, let us not merely say [MTY] that [we love our fellow believers!] Let us genuinely/really love them by doing things [to help them]!
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi ọ̀rọ̀ tàbí ahọ́n fẹ́ràn, bí kò ṣe ni ìṣe àti ní òtítọ́.
19 When we [truly love our fellow believers], we can be sure that we are [conducting our lives according to] the true message. [As a result], we will not feel guilty/ashamed [when we talk] [MTY] to God.
Àti nípa èyí ni àwa ó mọ̀ pé àwa jẹ́ ti òtítọ́, àti pé àwa ó sì fi ọkàn ara wa balẹ̀ níwájú rẹ̀.
20 [We can pray confidently], because [although] we might feel guilty/ashamed [about our sins], God is (greater/more worthy to be trusted) than what we feel. He knows everything [about us].
Nínú ohunkóhun tí ọkàn wa bá ń dá wa lẹ́bi; nítorí pé Ọlọ́run tóbi ju ọkàn wa lọ, ó sì mọ ohun gbogbo.
21 Dear friends, when we do not feel guilty [because of our sins], we can pray to God confidently.
Olùfẹ́, bí ọkàn wa kò bá dá wa lẹ́bi, ǹjẹ́ àwa ni ìgboyà níwájú Ọlọ́run?
22 And, when we confidently pray to him and request [something from him], we receive it because we do what he commands [us to do], and because we do what pleases him.
Àti ohunkóhun tí àwa bá béèrè, ni àwa ń rí gbà lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí àwa ń pa òfin rẹ̀ mọ́, àwa sì ń ṣe àwọn nǹkan tí ó dára lójú rẹ̀.
23 [I will tell you] what he commands [us to do]: [We must] believe that Jesus Christ is (his Son/the one who is also God). [We must] also love each other, just like he commanded [us to do].
Èyí sì ni òfin rẹ̀, pé kí àwa gba orúkọ Jesu Kristi Ọmọ rẹ̀ gbọ́, kí a sì fẹ́ràn ara wá gẹ́gẹ́ bí ó tí fi òfin fún wa.
24 Those who do what God commands are ones who have a close relationship with God, and God has a close relationship with them. [I will tell you how] we can be sure that God has a close relationship with us: It is because [we have] his Spirit, whom he gave to us, that we can be sure that God has a close relationship with us.
Ẹni tí ó bá sì pa òfin rẹ̀ mọ́ ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú rẹ̀. Àti nípa èyí ni àwa mọ̀ pé ó ń gbé inú wa, nípa Ẹ̀mí tí ó fi fún wa.

< 1 John 3 >