< 1 Chronicles 21 >
1 Satan decided to cause the Israeli people to have trouble. So he incited David to find out how many men in Israel [were able to be in the army].
Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
2 So David commanded Joab and the other army commanders, “Count all the men in Israel [who are able to be in the army]. Start at Beersheba [town in the south] and go all the way to Dan [city in the north]. Then come back and report to me, in order that I may know how many men there are.”
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
3 But Joab replied, “Your majesty, even if Yahweh allowed us to have 100 times as many soldiers as we have now, you would [RHQ] still rule all of them. So why do you want us to do this? You will surely [RHQ] cause [all the people of] Israel to be guilty of sinning.”
Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
4 But David would not change his mind. So Joab [and his soldiers] went everywhere in Israel and in Judah, and counted the people. Then they returned to Jerusalem,
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
5 and they reported to David that there were 1,100,000 men in Israel who could be in the army, and 470,000 in Judah.
Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
6 Joab did not count the men from the tribes of Levi and Benjamin, because he was disgusted with what the king had commanded.
Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
7 David’s command to count the people caused God to become angry, so he [told David that he had decided to] punish [the people of] Israel.
Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
8 Then David prayed, saying, “Yahweh, what I did was very foolish. I have sinned greatly by what I have done. So now I plead with you, please forgive me.”
Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
9 Then Yahweh said to Gad, David’s prophet,
Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
10 “Go and tell this to David: I am allowing you to choose one of three things [to punish you]. I will do whichever one you choose.”
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
11 So Gad went to David and said to him, “This is what Yahweh says: ‘You can choose one of these [punishments]:
Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
12 three years of famine [in Israel], or three months during which your armies will run away from their enemies [who will attack them with] swords, or three days during which I will send my angel to cause many people in the country to die because of a (plague/very serious illness).’ So, you must decide what I will say to answer [Yahweh, ] the one who sent me.”
Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
13 David replied to Gad, “I am very distressed. But allow Yahweh to punish [MTY] me, because he is very merciful. Do not allow humans to punish me, [because they will not be merciful].”
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
14 So Yahweh sent a plague on [the people of] Israel, and 70,000 of them died because of it.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
15 And God sent an angel to destroy the people in Jerusalem by the plague. But when the angel was standing at the ground where Araunah, from the Jebus people-group, threshed grain, Yahweh saw all the suffering that the people had endured, and he was grieved. So he said to the angel, “Stop what you are doing [IDM]! That is enough [IDM]!”
Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
16 David looked up and saw the angel whom Yahweh had sent, standing between the sky and the ground. The angel had a sword in his hand that was pointed toward Jerusalem. Then David and the elders [of the city], who were wearing clothes made of rough sackcloth, prostrated themselves on the ground.
Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
17 David said to God, “I am [RHQ] the one who ordered the men who could be in the army to be counted. I am the one who has sinned and done what is very wrong, but these people are [as innocent as] [MET] sheep. They have certainly not [RHQ] done anything [that is wrong]. So Yahweh my God, punish [IDM] me and my family, but do not allow this plague to continue to [cause] your people [to become sick and die].”
Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
18 Then the angel who was sent by Yahweh told Gad to go up to the place where Araunah threshed grain and tell David to build an altar to [worship] Yahweh there.
Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
19 So [after Gad told] David, [he] obeyed the message that Yahweh [MTY] had given to Gad, [and he went up there].
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
20 While Araunah was threshing some wheat, he turned and saw the angel. His four sons who were with him [also saw the angel, and they] hid themselves.
Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
21 Then David approached. When Araunah saw him, he left the place where he was threshing grain and prostrated himself, with his face touching the ground.
Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
22 David said to him, “Please sell me your threshing place in order that I can build an altar here to [worship] Yahweh. Then he will stop this plague. I will pay the full price.”
Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
23 Araunah replied, “Take it! Your majesty, do whatever you want to. I will give you the oxen [that thresh the grain] for an offering to be completely burned [on the altar]. And I will give you the threshing boards to use as wood [on the altar], and I will give you grain for a grain offering. I will give all those things to you.”
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
24 But the king said to Araunah, “No, [I will not take these things as a gift]. I will pay you the full price for it. I will not take things that belong to you, things that have cost me nothing and offer them as sacrifices to Yahweh to be completely burned on the altar.”
Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
25 So David paid Araunah 600 pieces of gold for the whole area.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
26 David built an altar to [worship] Yahweh there, and he offered sacrifices to be completely burned [on the altar] and sacrifices to restore fellowship [with Yahweh]. David prayed to Yahweh, and Yahweh answered by sending a fire from heaven [to burn up the offerings] on the altar.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
27 Then Yahweh spoke to the angel, and told him to put his sword back into its sheath. [So the angel did that].
Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
28 And when David saw that Yahweh had answered him there at the place where Araunah threshed grain [and had ended the plague], he offered sacrifices there.
Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
29 Yahweh’s Sacred Tent, which Moses had commanded to be set up in the desert, and the altar for burning sacrifices completely, were at that time on a hill at Gibeon [city].
Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
30 But David did not want to go there to request God to tell him what he wanted [him to do], because he was afraid that the angel sent from Yahweh [might strike him with] his sword.
Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.