< Ezekiel 14 >
1 and to come (in): come to(wards) me human from old: elder Israel and to dwell to/for face: before my
Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
2 and to be word LORD to(wards) me to/for to say
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
3 son: child man [the] human [the] these to ascend: establish idol their upon heart their and stumbling iniquity: crime their to give: put before face their to seek to seek to/for them
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
4 to/for so to speak: speak with them and to say to(wards) them thus to say Lord YHWH/God man man from house: household Israel which to ascend: establish [obj] idol his to(wards) heart his and stumbling iniquity: crime his to set: make before face his and to come (in): come to(wards) [the] prophet I LORD to answer to/for him (to come (in): come *Q(K)*) in/on/with abundance idol his
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
5 because to capture [obj] house: household Israel in/on/with heart their which be a stranger from upon me in/on/with idol their all their
Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
6 to/for so to say to(wards) house: household Israel thus to say Lord YHWH/God to return: repent and to return: repent from upon idol your and from upon all abomination your to return: turn back face your
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
7 for man man from house: household Israel and from [the] sojourner which to sojourn in/on/with Israel and to dedicate from after me and to ascend: establish idol his to(wards) heart his and stumbling iniquity: crime his to set: put before face his and to come (in): come to(wards) [the] prophet to/for to seek to/for him in/on/with me I LORD to answer to/for him in/on/with me
“‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
8 and to give: put face my in/on/with man [the] he/she/it and to set: make him to/for sign: indicator and to/for proverb and to cut: eliminate him from midst people my and to know for I LORD
Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
9 and [the] prophet for to entice and to speak: speak word I LORD to entice [obj] [the] prophet [the] he/she/it and to stretch [obj] hand: power my upon him and to destroy him from midst people my Israel
“‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
10 and to lift: guilt iniquity: punishment their like/as iniquity: punishment [the] to seek like/as iniquity: punishment [the] prophet to be
Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 because not to go astray still house: household Israel from after me and not to defile still in/on/with all transgression their and to be to/for me to/for people and I to be to/for them to/for God utterance Lord YHWH/God
Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
12 and to be word LORD to(wards) me to/for to say
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
13 son: child man land: country/planet for to sin to/for me to/for be unfaithful unfaithfulness and to stretch hand: power my upon her and to break to/for her tribe: supply food: bread and to send: depart in/on/with her famine and to cut: eliminate from her man and animal
“Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
14 and to be three [the] human [the] these in/on/with midst her Noah (Daniel *Q(K)*) and Job they(masc.) in/on/with righteousness their to rescue soul: life their utterance Lord YHWH/God
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
15 if living thing bad: harmful to pass in/on/with land: country/planet and be bereaved her and to be devastation from without to pass from face: because [the] living thing
“Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
16 three [the] human [the] these in/on/with midst her alive I utterance Lord YHWH/God if: surely no son: child and if: surely no daughter to rescue they(masc.) to/for alone them to rescue and [the] land: country/planet to be devastation
bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
17 or sword to come (in): bring upon [the] land: country/planet [the] he/she/it and to say sword to pass in/on/with land: country/planet and to cut: eliminate from her man and animal
“Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
18 and three [the] human [the] these in/on/with midst her alive I utterance Lord YHWH/God not to rescue son: child and daughter for they(masc.) to/for alone them to rescue
Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
19 or pestilence to send: depart to(wards) [the] land: country/planet [the] he/she/it and to pour: pour rage my upon her in/on/with blood to/for to cut: eliminate from her man and animal
“Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20 and Noah (Daniel *Q(K)*) and Job in/on/with midst her alive I utterance Lord YHWH/God if: surely no son: child if: surely no daughter to rescue they(masc.) in/on/with righteousness their to rescue soul: life their
bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
21 for thus to say Lord YHWH/God also for four judgment my [the] bad: harmful sword and famine and living thing bad: harmful and pestilence to send: depart to(wards) Jerusalem to/for to cut: eliminate from her man and animal
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22 and behold to remain in/on/with her survivor [the] to come out: send son: child and daughter look! they to come out: come to(wards) you and to see: see [obj] way: conduct their and [obj] wantonness their and to be sorry: comfort upon [the] distress: harm which to come (in): bring upon Jerusalem [obj] all which to come (in): bring upon her
Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23 and to be sorry: comfort [obj] you for to see: see [obj] way: conduct their and [obj] wantonness their and to know for not for nothing to make: do [obj] all which to make: do in/on/with her utterance Lord YHWH/God
Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”