< Zechariah 8 >

1 And it came [the] word of Yahweh of hosts saying.
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
2 Thus he says Yahweh of hosts I am jealous for Zion jealousy great and rage great I am jealous for it.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
3 Thus he says Yahweh I have returned to Zion and I will dwell in [the] midst of Jerusalem and it will be called Jerusalem [the] city of faithfulness and [the] mountain of Yahweh of hosts [the] mountain of holiness.
Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
4 Thus he says Yahweh of hosts again they will sit old [men] and old [women] in [the] open places of Jerusalem and each staff his [will be] in hand his from abundance of days.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
5 And [the] open places of the city they will be filled boys and girls playing in open places its.
Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
6 Thus he says Yahweh of hosts if it will be difficult in [the] eyes of [the] remnant of the people this in the days those also in view my will it be difficult? [the] utterance of Yahweh of hosts.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Thus he says Yahweh of hosts here I [am] about to save people my from [the] land of [the] east and from [the] land of [the] setting of the sun.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
8 And I will bring them and they will dwell in [the] midst of Jerusalem and they will become for me a people and I I will become for them God in faithfulness and in righteousness.
Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
9 Thus he says Yahweh of hosts let them be strong hands your O those [who] hear in the days these the words these from [the] mouth of the prophets who on [the] day [when] it was founded [the] house of Yahweh of hosts the temple to be rebuilt.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
10 For before the days those [the] wage[s] of person not it happened and [the] wage[s] of the animal[s] [was] not it and [belonged] to the [one who] went out and to the [one who] came not peace from the opponent so I may send every person each on neighbor his.
Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
11 And now not like the days former I [will be] to [the] remnant of the people this [the] utterance of Yahweh of hosts.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 That [the] seed of peace the vine it will give fruit its and the land it will give produce its and the heavens they will give dew their and I will give as an inheritance [the] remnant of the people this all these [things].
“Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
13 And it will be just as you were a curse among the nations O house of Judah and [the] house of Israel so I will save you and you will be a blessing may not you be afraid let them be strong hands your.
Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
14 For thus he says Yahweh of hosts just as I planned to do harm to you when provoked to anger ancestors your me he says Yahweh of hosts and not I relented.
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
15 So I have returned I have planned in the days these to do good to Jerusalem and [the] house of Judah may not you be afraid.
“Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
16 These [are] the things which you will do speak truth each with neighbor his faithfulness and justice of peace judge in gates your.
Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
17 And each - [the] harm of neighbor his may not you plan in heart your and an oath of falsehood may not you love for all these [are things] which I hate [the] utterance of Yahweh.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
18 And it came [the] word of Yahweh of hosts to me saying.
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
19 Thus he says Yahweh of hosts [the] fast of the fourth [month] and [the] fast of the fifth [month] and [the] fast of the seventh [month] and [the] fast of the tenth [month] it will become for [the] house of Judah joy and gladness and appointed feasts good and truth and peace love.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
20 Thus he says Yahweh of hosts yet this: they will come peoples and [the] inhabitants of cities many.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
21 And they will go [the] inhabitants of one [city] to one [city] saying let us go steadfastly to entreat [the] face of Yahweh and to seek Yahweh of hosts I will go also I.
Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
22 And they will come peoples many and nations mighty to seek Yahweh of hosts in Jerusalem and to entreat [the] face of Yahweh.
Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
23 Thus he says Yahweh of hosts in the days those that they will take hold ten people from all [the] tongues of the nations and they will take hold on [the] skirt of a person Jewish saying we want to go with you for we have heard God [is] with you.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”

< Zechariah 8 >