< Ruth 4 >

1 And Boaz he went up the gate and he sat down there and there! the kinsman-redeemer [was] passing by whom he had spoken Boaz and he said turn aside! sit! here a certain one a certain one and he turned aside and he sat down.
Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
2 And he took ten men from [the] elders of the city and he said sit here and they sat down.
Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
3 And he said to the kinsman redeemer [the] portion of the field which [belonged] to brother our to Elimelech she has sold Naomi who returned from [the] region of Moab.
ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
4 And I I said I will uncover ear your saying acquire [it] before the [ones] sitting and before [the] elders of people my if you will redeem redeem and if not he will redeem tell! to me (so let me know *Q(K)*) that there not except you [is] to redeem and I [am] after you and he said I I will redeem.
Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
5 And he said Boaz on [the] day acquiring you the field from [the] hand of Naomi and from with Ruth the Moabite [woman] [the] wife of the dead [man] (you have acquired *Q(K)*) to raise up [the] name of the dead [man] over inheritance his.
Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
6 And he said the kinsman-redeemer not I am able (to redeem [it] *Q(k)*) for myself lest I should ruin own inheritance my redeem for yourself you right of redemption my for not I am able to redeem [it].
Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
7 And this before [was] in Israel on the redemption and on the exchange to confirm every matter he took off anyone sandal his and he gave [it] to neighbor his and this [was] the attestation in Israel.
Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
8 And he said the kinsman-redeemer to Boaz acquire [it] for yourself and he took off sandal his.
Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
9 And he said Boaz to the elders and all the people [are] witnesses you this day that I acquire all that [belonged] to Elimelech and all that [belonged] to Kilion and Mahlon from [the] hand of Naomi.
Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
10 And also Ruth the Moabite [woman] [the] wife of Mahlon I acquire for myself to a wife to raise up [the] name of the dead [man] over inheritance his and not it will be cut off [the] name of the dead [man] from with brothers his and from [the] gate of place his [are] witnesses you this day.
Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
11 And they said all the people which [was] at the gate and the elders [we are] witnesses may he make Yahweh the woman who is about to come into house your like Rachel - and like Leah who they built [the] two of them [the] house of Israel and make wealth in Ephrathah and proclaim a name in Beth-lehem.
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
12 So may it be household your like [the] household of Perez whom she bore Tamar to Judah from the offspring which he will give Yahweh to you from the young woman this.
Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
13 And he took Boaz Ruth and she became of him a wife and he went into her and he gave Yahweh to her conception and she bore a son.
Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
14 And they said the women to Naomi [be] blessed Yahweh who not he has caused to cease to you a kinsman-redeemer this day and may it be proclaimed name his in Israel.
Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
15 And he will become for you [one who] restores life and to sustain old age your for daughter-in-law your who she loves you she has given birth to him who she [is] good to you more than seven sons.
Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
16 And she took Naomi the child and she placed him on bosom her and she became of him a nurse.
Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
17 And they called him the [female] neighbors a name saying he has been born a son to Naomi and they called name his Obed he [was] [the] father of Jesse [the] father of David.
Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
18 And these [are] [the] descendants of Perez Perez he fathered Hezron.
Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
19 And Hezron he fathered Ram and Ram he fathered Amminadab.
Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
20 And Amminadab he fathered Nahshon and Nahshon he fathered Salmah.
Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
21 And Salmon he fathered Boaz and Boaz he fathered Obed.
Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
22 And Obed he fathered Jesse and Jesse he fathered David.
Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.

< Ruth 4 >