< Psalms 88 >
1 A song a psalm of [the] sons of Korah to the choirmaster on Machalath to sing a poem of Heman the Ezrachite. O Yahweh [the] God of salvation my day I have cried out in the night before you.
Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti mahalati leannoti. Maskili ti Hemani ará Esra. Olúwa, Ọlọ́run tí ó gbà mí là, ní ọ̀sán àti ní òru, mo kígbe sókè sí Ọ.
2 May it come before you prayer my incline ear your to cry of entreaty my.
Jẹ́ kí àdúrà mi kí ó wá sí iwájú rẹ; dẹ etí rẹ sí igbe mi.
3 For it is surfeited with troubles being my and life my to Sheol they have reached. (Sheol )
Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njú ọkàn mi sì súnmọ́ isà òkú. (Sheol )
4 I am reckoned with [those who] go down of [the] pit I am like a man [whom] there not [is] strength.
A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀ èmi dàbí ọkùnrin tí kò ni agbára.
5 Among the dead a [person] set free like [those] slain - [who] lie of [the] grave whom not you remember them again and they from hand your they are cut off.
A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkú bí ẹni tí a pa tí ó dùbúlẹ̀ ní ipò ikú, ẹni tí ìwọ kò rántí mọ́, ẹni tí a gé kúrò lára àwọn tí ìwọ ń tọ́jú.
6 You have put me in a pit of lowest parts in [the] dark places in [the] depths.
Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jíjìn, ní ibi ọ̀gbun tó ṣókùnkùn.
7 On me it has lain anger your and all breakers your you have afflicted [me] (Selah)
Ìbínú rẹ ṣubú lé mi gidigidi; ìwọ ti fi àwọn ìjì rẹ borí mi.
8 You have removed far away acquaintances my from me you have made me abominations to them [I am] shut up and not I will go out.
Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mi kúrò lọ́wọ́ mi ìwọ sì sọ mi di ìríra sí wọn. A há mi mọ́, èmi kò sì le è jáde;
9 Eye my it is faint from affliction I have called out to you O Yahweh on every day I have spread out to you hands my.
ojú mi káàánú nítorí ìpọ́njú. Mo kígbe pè ọ́, Olúwa, ní gbogbo ọjọ́; mo na ọwọ́ mi jáde sí ọ.
10 ¿ For the dead will you do wonder[s] or? [the] shades will they arise - will they give thanks to? you (Selah)
Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ hàn fún òkú bi? Àwọn òkú yóò ha dìde láti yìn ọ́ bí?
11 ¿ Will it be recounted in the grave covenant loyalty your faithfulness your in Abaddon.
A ó ha fi ìṣeun ìfẹ́ rẹ hàn ní ibojì bí, tàbí òtítọ́ rẹ ní ipò ìparun?
12 ¿ Will it be known in the darkness wonder[s] your and righteousness your in [the] land of forgetting.
A ha lè mọ iṣẹ́ ìyanu rẹ ní òkùnkùn bí àti òdodo rẹ ní ilẹ̀ ìgbàgbé?
13 And I - to you O Yahweh I cry for help and in the morning prayer my it comes to meet you.
Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa; ní òwúrọ̀ ni àdúrà mí wá sọ́dọ̀ rẹ.
14 Why? O Yahweh do you reject self my do you hide? face your from me.
Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí tí ìwọ fi ojú rẹ pamọ́ fún mi?
15 [have been] afflicted I and [have been] about to die from youth I have borne terrors your I am perplexed.
Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi, èmi múra àti kú; nígbà tí ẹ̀rù rẹ bá ń bà mí, èmi di gbére-gbère.
16 Over me they have passed anger your terrors your they have destroyed me.
Ìbínú rẹ ti kọjá lára mi; ìbẹ̀rù rẹ ti gé mi kúrò.
17 They have surrounded me like water all the day they have surrounded me altogether.
Ní gbogbo ọjọ́ ni wọn yí mi ká bí ìkún omi; wọ́n mù mí pátápátá.
18 You have removed far away from me [one who] loves and a friend acquaintances my darkness.
Ìwọ ti mú ọ̀rẹ́ àti olùfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi; òkùnkùn sì jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi.