< Psalms 111 >

1 Praise Yahweh - I will give thanks to Yahweh with all [the] heart in [the] council of upright [people] and [the] congregation.
Ẹ máa yin Olúwa. Èmi yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi, ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.
2 [are] great [the] works of Yahweh [they are] studied by all [those] delighting in them.
Iṣẹ́ Olúwa tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.
3 [is] splendor And majesty work his and righteousness his [is] enduring for ever.
Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo: àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.
4 Remembrance he has appointed of wonders his [is] gracious and compassionate Yahweh.
Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí: Olúwa ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.
5 Food he gives to [those] fearing him he remembers for ever covenant his.
Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀: òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.
6 [the] power of Works his he has declared to people his to give to them an inheritance of nations.
Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀ láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.
7 [the] works of Hands his [are] faithfulness and justice [are] reliable all precepts his.
Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.
8 [they are] sustained For ever for ever [they are] done in faithfulness and upright[ness].
Wọ́n dúró láé àti láé, ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.
9 Redemption - he sent for people his he ordained for ever covenant his [is] holy and to be feared name his.
Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀: ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé, mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.
10 [is the] beginning of Wisdom - [the] fear of Yahweh an understanding good [belongs] to all [those who] do them praise his [is] enduring for ever.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n: òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀, ìyìn rẹ̀ dúró láé.

< Psalms 111 >