< Psalms 108 >
1 A song a psalm of David. [is] steadfast Heart my O God I will sing and I will sing praises also honor my.
Orin. Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
2 Awake! O lyre and harp I will waken [the] dawn.
Jí ohun èlò orin àti haapu! Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
3 I will give thanks you among the peoples - O Yahweh and I will sing praises to you not nations.
èmi ó yìn ọ́, Olúwa, nínú àwọn orílẹ̀-èdè, èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
4 For [is] great above [the] heavens covenant loyalty your and [is] to [the] clouds faithfulness your.
Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ ju àwọn ọ̀run lọ àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
5 Be exalted! above [the] heavens O God and [be] over all the earth glory your.
Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run, àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
6 So that they may be rescued! beloved [ones] your save! right [hand] your and answer me.
Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là; fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà, kí o sì dá mi lóhùn
7 God - he has spoken in sanctuary his I will triumph I will divide up Shechem and [the] Valley of Succoth I will measure off.
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu, èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
8 [belongs] to Me Gilead - [belongs] to me Manasseh and Ephraim [is] [the] protection of head my Judah [is] commander's staff my.
Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi, Efraimu ni ìbòrí mi, Juda ni olófin mi,
9 Moab - [is] [the] pot of washing my over Edom I throw sandal my over Philistia I shout in triumph.
Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí, lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
10 Who? will he bring me a city of fortification who? will he lead me to Edom.
Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi? Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
11 ¿ Not O God have you rejected us and not you go out O God with armies our.
Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀. Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
12 Give! to us help from [the] foe and [is] worthlessness [the] deliverance of humankind.
Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú, nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
13 In God we will do strength and he he will tread down opponents our.
Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.