< Numbers 2 >
1 And he spoke Yahweh to Moses and to Aaron saying.
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Everyone at standard his with [the] signs of [the] house of ancestors their they will encamp [the] people of Israel from before around [the] tent of meeting they will encamp.
“Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
3 And those [who] encamp east-ward east-ward [will be] [the] standard of [the] camp of Judah to military groups their and [the] leader of [the] descendants of Judah [was] Nahshon [the] son of Amminadab.
Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
4 And military group his and enrolled [men] their [were] four and seventy thousand and six hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
5 And those [who] encamp on him [will be] [the] tribe of Issachar and [the] leader of [the] descendants of Issachar [was] Nethanel [the] son of Zuar.
Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
6 And military group his and enrolled [men] his [were] four and fifty thousand and four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
7 [the] tribe of Zebulun and [the] leader of [the] descendants of Zebulun [was] Eliab [the] son of Helon.
Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
8 And military group his and enrolled [men] his [were] seven and fifty thousand and four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
9 All those enrolled of [the] camp of Judah [were] one hundred thousand and eighty thousand and six thousand and four hundred to military groups their first they will set out.
Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
10 [the] standard of [the] camp of Reuben [will be] south-ward to military groups their and [the] leader of [the] descendants of Reuben [was] Elizur [the] son of Shedeur.
Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
11 And military group his and enrolled [men] his [were] six and forty thousand and five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
12 And those [who] encamp on him [will be] [the] tribe of Simeon and [the] leader of [the] descendants of Simeon [was] Shelumiel [the] son of Zuri-shaddai.
Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
13 And military group his and enrolled [men] their [were] nine and fifty thousand and three hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
14 And [the] tribe of Gad and [the] leader of [the] descendants of Gad [was] Eliasaph [the] son of Reuel.
Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
15 And military group his and enrolled [men] their [were] five and forty thousand and six hundred and fifty.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
16 All those enrolled of [the] camp of Reuben [were] one hundred thousand and one and fifty thousand and four hundred and fifty to military groups their and second they will set out.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
17 And it will set out [the] tent of meeting [the] camp of the Levites [will be] in [the] middle of the camps just as they will encamp so they will set out each on hand his to standards their.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
18 [the] standard of [the] camp of Ephraim to military groups their [will be] west-ward and [the] leader of [the] descendants of Ephraim [was] Elishama [the] son of Ammihud.
Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
19 And military group his and enrolled [men] their [were] forty thousand and five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
20 And [will be] on him [the] tribe of Manasseh and [the] leader of [the] descendants of Manasseh [was] Gamaliel [the] son of Pedahzur.
Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
21 And military group his and enrolled [men] their [were] two and thirty thousand and two hundred.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
22 And [the] tribe of Benjamin and [the] leader of [the] descendants Benjamin [was] Abidan [the] son of Gideoni.
Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
23 And military group his and enrolled [men] their [were] five and thirty thousand and four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
24 All those enrolled of [the] camp of Ephraim [were] one hundred thousand and eight thousand and one hundred to military groups their and third they will set out.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
25 [the] standard of [the] camp of Dan [will be] north-ward to military groups their and [the] leader of [the] descendants of Dan [was] Ahiezer [the] son of Ammishaddai.
Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
26 And military group his and enrolled [men] their [were] two and sixty thousand and seven hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
27 And those [who] encamp on him [will be] [the] tribe of Asher and [the] leader of [the] descendants of Asher [was] Pagiel [the] son of Ocran.
Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
28 And military group his and enrolled [men] their [were] one and forty thousand and five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
29 And [the] tribe of Naphtali and [the] leader of [the] descendants of Naphtali [was] Ahira [the] son of Enan.
Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
30 And military group his and enrolled [men] their [were] three and fifty thousand and four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
31 All those enrolled of [the] camp of Dan [were] one hundred thousand and seven and fifty thousand and six hundred to the last they will set out to standards their.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
32 These [were] [the] [men] enrolled of [the] people of Israel to [the] house of ancestors their all [those] enrolled of the camps to military groups their [were] six hundred thousand and three thousand and five hundred and fifty.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
33 And the Levites not they were enrolled in among [the] people of Israel just as he had commanded Yahweh Moses.
Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
34 And they did [the] people of Israel according to all that he had commanded Yahweh Moses so they camped to standards their and so they set out everyone to clans his on [the] house of ancestors his.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.