< Nehemiah 11 >

1 And they dwelt [the] leaders of the people in Jerusalem and [the] rest of the people they cast lots to bring - one of the ten to dwell in Jerusalem [the] city of holiness and nine the hands [were] in the cities.
Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
2 And they blessed the people all the men who volunteered to dwell in Jerusalem.
Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
3 And these [are] [the] leaders of the province who they dwelt in Jerusalem and in [the] cities of Judah they dwelt each one on own property his in own cities their Israel the priests and the Levites and the temple servants and [the] descendants of [the] servants of Solomon.
Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
4 And in Jerusalem they dwelt some of [the] descendants of Judah and some of [the] descendants of Benjamin of [the] descendants of Judah Athaiah [the] son of Uzziah [the] son of Zechariah [the] son of Amariah [the] son of Shephatiah [the] son of Mahalalel of [the] descendants of Perez.
Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
5 And Maaseiah [the] son of Baruch [the] son of Col-Hozeh [the] son of Hazaiah [the] son of Adaiah [the] son of Joiarib [the] son of Zechariah [the] son of the Shilonite.
àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
6 All [the] descendants of Perez who were dwelling in Jerusalem four hundred sixty and eight men of strength.
Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
7 And these [are] [the] descendants of Benjamin Sallu [the] son of Meshullam [the] son of Joed [the] son of Pedaiah [the] son of Kolaiah [the] son of Maaseiah [the] son of Ithiel [the] son of Jeshaiah.
Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
8 And after him Gabbai Sallai nine hundred twenty and eight.
àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
9 And Joel [the] son of Zikri [was] overseer over them and Judah [the] son of Senaah over the city [was] second in command.
Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
10 Of the priests Jedaiah [the] son of Joiarib Jakin.
Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
11 Seraiah [the] son of Hilkiah [the] son of Meshullam [the] son of Zadok [the] son of Meraioth [the] son of Ahitub [the] supervisor of [the] house of God.
Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
12 And brothers their [who] did the work of the house eight hundred twenty and two and Adaiah [the] son of Jeroham [the] son of Pelaliah [the] son of Amzi [the] son of Zechariah [the] son of Pashhur [the] son of Malkijah.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
13 And brothers his leaders of fathers two hundred forty and two and Amashsai [the] son of Azarel [the] son of Ahzai [the] son of Meshillemoth [the] son of Immer.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
14 And brothers their mighty [men] of strength one hundred twenty and eight and [was] overseer over them Zabdiel [the] son of (Haggedolim. *L(F)*)
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
15 And of the Levites Shemaiah [the] son of Hasshub [the] son of Azrikam [the] son of Hashabiah [the] son of Bunni.
Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
16 And Shabbethai and Jozabad over the work external of [the] house of God [were] of [the] leaders of the Levites.
Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
17 And Mattaniah [the] son of Micah [the] son of Zabdi [the] son of Asaph [the] leader of the beginning he gave thanks to the prayer and Bakbukiah [the] second from brothers his and Abda [the] son of Shammua [the] son of Galal [the] son of (Jeduthun. *Q(K)*)
Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
18 All the Levites in [the] city of holiness two hundred eighty and four.
Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
19 And the gatekeepers Akkub Talmon and brothers their who kept watch at the gates one hundred seventy and two.
Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
20 And [the] rest of Israel the priests the Levites [were] in all [the] cities of Judah each one on own inheritance his.
Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
21 And the temple servants [were] dwelling on Ophel and Ziha and Gishpa [were] over the temple servants.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
22 And [the] overseer of the Levites in Jerusalem [was] Uzzi [the] son of Bani [the] son of Hashabiah [the] son of Mattaniah [the] son of Mica one of [the] descendants of Asaph the singers to before [the] work of [the] house of God.
Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
23 For [the] commandment of the king [was] on them and a firm ordinance [was] on the singers [the] matter of a day in day its.
Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
24 And Pethahiah [the] son of Meshezabel one of [the] descendants of Zerah [the] son of Judah [was] to [the] side of the king to every matter of the people.
Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
25 And to the villages with fields their some of [the] people of Judah they dwelt in Kiriath Arba and daughters its and in Dibon and daughters its and in Jekabzeel and villages its.
Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
26 And in Jeshua and in Moladah and in Beth Pelet.
Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
27 And in Hazar Shual and in Beer Sheba and daughters its.
ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
28 And in Ziklag and in Meconah and in daughters its.
Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
29 And in En Rimmon and in Zorah and in Jarmuth.
ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
30 Zanoah Adullam and villages their Lachish and fields its Azekah and daughters its and they encamped from Beer Sheba to [the] valley of [Ben] Hinnom.
Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
31 And [the] descendants of Benjamin [were] from Geba Micmash and Aija and Beth-el and daughters its.
Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
32 Anathoth Nob Ananiah.
Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
33 Hazor - Ramah Gittaim.
ní Hasori Rama àti Gittaimu,
34 Hadid Zeboim Neballat.
ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
35 Lod and Ono valley of the craftsmen.
ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
36 And some of the Levites [the] divisions of Judah [belonged] to Benjamin.
Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.

< Nehemiah 11 >