< Judges 4 >
1 And they repeated [the] people of Israel to do the evil in [the] eyes of Yahweh and Ehud he had died.
Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
2 And he sold them Yahweh in [the] hand of Jabin [the] king of Canaan who he reigned in Hazor and [was] [the] commander of army his Sisera and he [was] dwelling in Harosheth Haggoyim.
Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
3 And they cried out [the] people of Israel to Yahweh for nine hundred chariot[s] of iron [belonged] to him and he he oppressed [the] people of Israel with force twenty year[s].
Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
4 And Deborah a woman a prophetess [the] wife of Lappidoth she [was] judging Israel at the time that.
Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
5 And she [was] dwelling under [the] palm tree of Deborah between Ramah and between Beth-el in [the] hill country of Ephraim and they went up to her [the] people of Israel for judgment.
Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
6 And she sent and she summoned Barak [the] son of Abinoam from Kedesh Naphtali and she said to him ¿ not has he commanded - Yahweh [the] God of Israel go and you will march at [the] mountain of Tabor and you will take with you ten thousand man from [the] descendants of Naphtali and of [the] descendants of Zebulun.
Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
7 And I will draw to you to [the] wadi of Kishon Sisera [the] commander of [the] army of Jabin and chariotry his and multitude his and I will give him in hand your.
Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
8 And he said to her Barak if you will go with me and I will go and if not you will go with me not I will go.
Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
9 And she said certainly I will go with you nevertheless for not it will be honor your on the way which you [are] going for in [the] hand of a woman he will sell Yahweh Sisera and she rose Deborah (and she went *L(abh)*) with Barak Kedesh towards.
Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
10 And he summoned Barak Zebulun and Naphtali Kedesh towards and it went up at feet his ten thousand man and she went up with him Deborah.
Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
11 And Heber the Kenite [was] separate from [the] Kenite[s] from [the] descendants of Hobab [the] father-in-law of Moses and he had pitched tent his to [the] great tree (in Zaanannim *Q(K)*) which [is] with Kedesh.
Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
12 And people told to Sisera that he had gone up Barak [the] son of Abinoam [the] mountain of Tabor.
Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
13 And he summoned Sisera all chariotry his nine hundred chariot[s] of iron and all the people which [was] with him from Harosheth Haggoyim to [the] wadi of Kishon.
Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
14 And she said Deborah to Barak arise for this [is] the day which he has given Yahweh Sisera in hand your ¿ not Yahweh has he gone out before you and he went down Barak from [the] mountain of Tabor and ten thousand man [were] after him.
Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
15 And he routed Yahweh Sisera and all the chariotry and all the army to [the] mouth of [the] sword before Barak and he went down Sisera from on the chariot and he fled on feet his.
Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
16 And Barak he pursued after the chariotry and after the army to Harosheth Haggoyim and it fell all [the] army of Sisera to [the] mouth of [the] sword not it was left up to one.
Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
17 And Sisera he fled on feet his to [the] tent of Jael ([the] wife of *L(abh)*) Heber the Kenite for peace [was] between Jabin [the] king of Hazor and between [the] house of Heber the Kenite.
Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
18 And she went out Jael to meet Sisera and she said to him turn aside! O lord my turn aside! to me may not you be afraid and he turned aside to her the tent towards and she covered him with the covering.
Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
19 And he said to her give to drink me please a little of water for I am thirsty and she opened [the] skin-bottle of milk and she gave a drink him and she covered him.
Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
20 And he said to her stand [the] opening of the tent and it will be if anyone he will come and he will ask you and he will say ¿ [is] there here anyone and you will say no.
Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
21 And she took Jael [the] wife of Heber [the] peg of the tent and she put the hammer in hand her and she went to him in secrecy and she drove the peg in temple his and it went down in the ground and he [was] sleeping and he was weary and he died.
Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
22 And there! Barak [was] pursuing Sisera and she went out Jael to meet him and she said to him come and I will show you the man whom you [are] seeking and he went to her and there! Sisera [was] lying dead and the peg [was] in temple his.
Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
23 And he subdued God on the day that Jabin [the] king of Canaan before [the] people of Israel.
Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
24 And it went [the] hand of [the] people of Israel going and hard on Jabin [the] king of Canaan until that they cut off Jabin [the] king of Canaan.
Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.