< Judges 13 >

1 And they repeated [the] people of Israel to do the evil in [the] eyes of Yahweh and he gave them Yahweh in [the] hand of [the] Philistines forty year[s].
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Olúwa sì fi wọ́n lé àwọn ará Filistini lọ́wọ́ fún ogójì ọdún.
2 And he was a man one from Zorah from [the] clan of the Danite[s] and name his [was] Manoah and wife his [was] barren and not she had borne children.
Ọkùnrin ará Sora kan wà, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Manoa láti ẹ̀yà Dani. Aya rẹ̀ yàgàn kò sì bímọ.
3 And he appeared [the] angel of Yahweh to the woman and he said to her here! please you [are] barren and not you have borne children and you will conceive and you will bear a son.
Angẹli Olúwa fi ara han obìnrin náà, ó sì wí fún un pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yàgàn, ìwọ kò sì tí ì bímọ, ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.
4 And therefore take care please and may not you drink wine and strong drink and may not you eat any unclean [thing].
Báyìí rí i dájúdájú pé ìwọ kò mu wáìnì tàbí ọtí líle kankan àti pé ìwọ kò jẹ ohun aláìmọ́ kankan,
5 For here you [will be] pregnant and you will bear a son and a razor not it will go up on head his for a Nazirite of God he will be the lad from the womb and he he will begin to deliver Israel from [the] hand of [the] Philistines.
nítorí ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Má ṣe fi abẹ kan orí rẹ̀, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀. Òun ni yóò bẹ̀rẹ̀ ìdáǹdè àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ọwọ́ àwọn ará Filistini.”
6 And she went the woman and she said to husband her saying man of God he came to me and appearance his [was] like [the] appearance of angel of God awesome very and not I asked him where? from this [was] he and name his not he told to me.
Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ angẹli Ọlọ́run, ó ba ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.
7 And he said to me here you [will be] pregnant and you will bear a son and therefore may not you drink - wine and strong drink and may not you eat any uncleanness for a Nazirite of God he will be the lad from the womb until [the] day of death his.
Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má ṣe jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Nasiri Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’”
8 And he prayed Manoah to Yahweh and he said pardon me O Lord [the] man of God whom you sent let him come please again to us so he may teach us what? will we do for the lad who is about to be born.
Nígbà náà ni Manoa gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”
9 And he listened God to [the] voice of Manoah and he came [the] angel of God again to the woman and she [was] sitting in the field and Manoah husband her not [was] with her.
Ọlọ́run fetí sí ohùn Manoa, angẹli Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Manoa kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
10 And she made haste the woman and she ran and she told to husband her and she said to him here! he has presented himself to me the man who he came on the day to me.
Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fi ara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”
11 And he arose and he went Manoah after wife his and he came to the man and he said to him ¿ [are] you the man who you spoke to the woman and he said I.
Manoa yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?” Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Èmi ni.”
12 And he said Manoah now it will come words your what? will it be [the] manner of the lad and work his.
Manoa bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”
13 And he said [the] angel of Yahweh to Manoah from all that I said to the woman she will take care.
Angẹli Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un
14 Any of all that it comes forth from [the] vine of the wine not she will eat and wine and strong drink may not she drink and any uncleanness may not she eat all that I commanded her she will keep.
kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èso àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pàṣẹ fún un.”
15 And he said Manoah to [the] angel of Yahweh let us detain please you so we may prepare before you a kid of goats.
Manoa sọ fún angẹli Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèsè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”
16 And he said [the] angel of Yahweh to Manoah if you will detain me not I will eat in food your and if you will make a burnt offering to Yahweh you will offer up it for not he knew Manoah that [was] [the] angel Yahweh it.
Angẹli Olúwa náà dá Manoa lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹ̀yin yóò pèsè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèsè ọrẹ ẹbọ sísun, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sí Olúwa.” (Manoa kò mọ̀ pé angẹli Olúwa ní i ṣe.)
17 And he said Manoah to [the] angel of Yahweh who? [is] name your if it will come (word your *Q(K)*) and we will honor you.
Manoa sì béèrè lọ́wọ́ angẹli Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”
18 And he said (to him *L(abh)*) [the] angel of Yahweh why? this are you asking to name my and it [is] incomprehensible.
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa náà dáhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ ń béèrè orúkọ mi? Ìyanu ni, ó kọjá ìmọ̀.”
19 And he took Manoah [the] kid of the goats and the grain offering and he offered [it] up on the rock to Yahweh and an extraordinary thing to do and Manoah and wife his [were] looking.
Lẹ́yìn náà ni Manoa mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọkà, ó sì fi rú ẹbọ lórí àpáta kan sí Olúwa. Nígbà tí Manoa àti ìyàwó dúró tí wọn ń wò Olúwa ṣe ohun ìyanu kan.
20 And it was when went up the flame from on the altar the heavens towards and he went up [the] angel of Yahweh in [the] flame of the altar and Manoah and wife his [were] looking and they fell on faces their [the] ground towards.
Bí ẹ̀là ahọ́n iná ti là jáde láti ibi pẹpẹ ìrúbọ náà sí ọ̀run, angẹli Olúwa gòkè re ọ̀run láàrín ahọ́n iná náà. Nígbà tí wọ́n rí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Manoa àti aya rẹ̀ wólẹ̀ wọ́n sì dojúbolẹ̀.
21 And not he repeated again [the] angel of Yahweh to appear to Manoah and to wife his then he knew Manoah that [was] [the] angel of Yahweh it.
Nígbà tí angẹli Olúwa náà kò tún fi ara rẹ̀ han Manoa àti aya rẹ̀ mọ́, Manoa wá mọ̀ pé angẹli Olúwa ni.
22 And he said Manoah to wife his certainly we will die for God we have seen.
Manoa sọ fún aya rẹ̀ pé, “Dájúdájú àwa yóò kú nítorí àwa ti fi ojú rí Ọlọ́run.”
23 And she said to him wife his if he had desired Yahweh to kill us not he accepted from hand our a burnt offering and a grain offering and not he showed us all these [things] and about this time not he caused to hear us like this.
Ṣùgbọ́n ìyàwó rẹ̀ dáhùn pé, “Bí Olúwa bá ní èrò àti pa wá kò bá tí gba ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wa, tàbí fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn wá tó sọ nǹkan ìyanu yìí fún wa.”
24 And she bore the woman a son and she called name his Samson and he grew up the lad and he blessed him Yahweh.
Obìnrin náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Samsoni. Ọmọ náà dàgbà Olúwa sì bùkún un.
25 And it began [the] spirit of Yahweh to stir him in Mahaneh Dan between Zorah and between Eshtaol.
Ẹ̀mí Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ru sókè nígbà tí ó wà ní Mahane-Dani ní agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli.

< Judges 13 >