< Isaiah 37 >
1 And it was when heard the king Hezekiah and he tore clothes his and he covered himself with sackcloth and he went [the] house of Yahweh.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 And he sent Eliakim who [was] over the house and - Shebna the scribe and [the] elders of the priests covered with sackcloth to Isaiah [the] son of Amoz the prophet.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 And they said to him thus he says Hezekiah [is] a day of distress and rebuke and insult the day this for they have come children to birth and [is] strength there not for giving birth.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Perhaps he will hear Yahweh God your - [the] words of [the] chief commander whom he has sent him [the] king of Assyria - master his to taunt [the] God living and he will rebuke the words which he has heard Yahweh God your and you will lift up prayer for the remnant which is found.
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 And they came [the] servants of the king Hezekiah to Isaiah.
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 And he said to them Isaiah thus you will say! to master your thus - he says Yahweh may not you be afraid of the words which you have heard which they have blasphemed [the] servants of [the] king of Assyria me.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Here I [am] about to put in him a spirit and he will hear a report and he will return to own land his and I will make fall him by the sword in own land his.
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 And he returned [the] chief commander and he found [the] king of Assyria fighting on Libnah if he had heard that he had departed from Lachish.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 And he heard on Tirhakah [the] king of Cush saying he has come out to do battle with you and he heard and he sent messengers to Hezekiah saying.
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 Thus you will say! to Hezekiah [the] king of Judah saying may not he deceive you God your whom you [are] trusting in him saying not it will be given Jerusalem in [the] hand of [the] king of Assyria.
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Here! - you you have heard [that] which they have done [the] kings of Assyria to all the lands by totally destroying them and you will you be delivered?
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 ¿ Did they deliver them [the] gods of the nations which they destroyed ancestors my Gozan and Haran and Rezeph and [the] people of Eden who [were] in Telassar.
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Where? [is] [the] king of Hamath and [the] king of Arpad and [the] king of Lair Sepharvaim Hena and Ivvah.
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 And he took Hezekiah the letters from [the] hand of the messengers and he read it and he went up [the] house of Yahweh and he spread out it Hezekiah before Yahweh.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 And he prayed Hezekiah to Yahweh saying.
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 O Yahweh of hosts [the] God of Israel [who] sits the cherubim you he [are] God to alone you of all [the] kingdoms of the earth you you have made the heavens and the earth.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 Incline O Yahweh - ear your and hear open O Yahweh eyes your and see and hear all [the] words of Sennacherib which he has sent to taunt [the] God living.
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Truly O Yahweh they have made desolate [the] kings of Assyria all the lands and land their.
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 And they have put gods their in the fire for not [were] gods they that except [the] work of [the] hands of a person wood and stone and they destroyed them.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 And now O Yahweh God our save us from hand his so they may know all [the] kingdoms of the earth that you [are] Yahweh to alone you.
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 And he sent Isaiah [the] son of Amoz to Hezekiah saying thus he says Yahweh [the] God of Israel that you have prayed to me concerning Sennacherib [the] king of Assyria.
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 This [is] the word which he has spoken Yahweh on him she has despised you she has mocked you [the] virgin of [the] daughter of Zion behind you a head she has shaken [the] daughter of Jerusalem.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Whom? have you taunted and have you blasphemed? and on whom? have you raised a voice and have you lifted up? height eyes your against [the] holy [one] of Israel.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 By [the] hand of servants your you have taunted - [the] Lord and you have said with [the] abundance of chariotry my I I have gone up [the] height[s] of mountains [the] remotest parts of Lebanon so I may cut down [the] height of cedars its [the] choicest of pines its so I may come [to the] height of end its [the] forest of orchard its.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 I I have dug and I have drunk water so I may dry up with [the] sole of feet my all [the] canals of Egypt.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 ¿ Not have you heard from distant [time] it I appointed from days of antiquity and I planned it now I have brought it and you are [about] to make desolate heaps ruined cities fortified.
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 And inhabitants their [were] short of hand they were dismayed and they were ashamed they were [the] vegetation of [the] field and [the] greenery of vegetation grass of roofs and a field before standing grain.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 And sitting down your and going out you and coming in you I know and raging you against me.
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Because raging you against me and arrogance your it has come up in ears my and I will put hook my in nose your and bridle my on lips your and I will turn back you by the way which you came by it.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 And this for you [will be] the sign you will eat this year self-sown grain and in the year second self-seeded plant[s] and in the year third sow and reap and plant vineyards (and eat *Q(K)*) fruit their.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 And it will add [the] escaped remnant of [the] house of Judah which remains a root downwards and it will produce fruit upwards.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 For from Jerusalem it will go out a remnant and an escaped remnant from [the] mountain of Zion [the] zeal of Yahweh of hosts it will accomplish this.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Therefore thus he says Yahweh concerning [the] king of Assyria not he will come into the city this and not he will shoot there an arrow and not he will confront it a shield and not he will pour out on it a mound.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 By the way which he came by it he will return and into the city this not he will come [the] utterance of Yahweh.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 And I will defend the city this to deliver it for own sake my and for [the] sake of David servant my.
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 And he went out - [the] angel of Yahweh and he struck down in [the] camp of Assyria one hundred and eighty and five thousand and they rose early in the morning and there! all of them [were] corpses dead.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 And he set out and he went and he returned Sennacherib [the] king of Assyria and he remained in Nineveh.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 And it was he [was] bowing down [the] house of - Nisroch god his and Adrammelech and Sharezer sons his they struck down him with the sword and they they escaped [the] land of Ararat and he reigned Esar-haddon son his in place his.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.