< Genesis 34 >

1 And she went out Dinah [the] daughter of Leah whom she had borne to Jacob to look on [the] daughters of the land.
Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
2 And he saw her Shechem [the] son of Hamor the Hivite [the] chief of the land and he took her and he lay with with her and he humiliated her.
Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
3 And it cleaved self his to Dinah [the] daughter of Jacob and he loved the girl and he spoke to [the] heart of the girl.
Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
4 And he said Shechem to Hamor father his saying get for me the girl this to a wife.
Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
5 And Jacob he heard that he had defiled Dinah daughter his and sons his they were with livestock his in the field and he kept silent Jacob until came they.
Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
6 And he went out Hamor [the] father of Shechem to Jacob to speak with him.
Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
7 And [the] sons of Jacob they came from the field when heard they and they were indignant the men and it burned to them exceedingly for a disgraceful folly he had done in Israel by lying with [the] daughter of Jacob and thus not it is done.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
8 And he spoke Hamor with them saying Shechem son my it loves self his daughter your give please her to him to a wife.
Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
9 And intermarry with with us daughters your you will give to us and daughters our you will take for yourselves.
Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
10 And with us you will dwell and the land it will be before you dwell and go about in it and have possessions in it.
Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
11 And he said Shechem to father her and to brothers her let me find favor in view your and [that] which you will say to me I will give.
Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
12 Increase on me exceedingly a bride price and a gift so let me give [it] just as you will say to me and give to me the girl to a wife.
Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
13 And they answered [the] sons of Jacob Shechem and Hamor father his with deceit and they spoke that he had defiled Dinah sister their.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
14 And they said to them not we are able to do the thing this to give sister our to a man whom [belongs] to him a foreskin for [is] a reproach it to us.
Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
15 Only in this we will agree to you if you will be like us by being circumcised of you every male.
Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
16 And we will give daughters our to you and daughters your we will take for ourselves and we will dwell with you and we will become a people one.
Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
17 And if not you will listen to us by being circumcised and we will take daughter our and we will go.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
18 And they were good words their in [the] eyes of Hamor and in [the] eyes of Shechem [the] son of Hamor.
Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
19 And not he delayed the young man to do the thing for he delighted in [the] daughter of Jacob and he [was] honored more than all [the] household of father his.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
20 And he went Hamor and Shechem son his to [the] gate of city their and they spoke to [the] men of city their saying.
Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
21 The men these [are] at peace they with us and let them dwell in the land and let them go about in it and the land there! [is] broad of both hands before them daughters their we will take for ourselves to wives and daughters our we will give to them.
Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 Only in this they will agree to us the men to dwell with us to become a people one when has been circumcised of us every male just as they [are] circumcised.
Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
23 Livestock their and possession[s] their and all animal[s] their ¿ not [belong] to us [will] they only let us agree with them and let them dwell with us.
Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
24 And they listened to Hamor and to Shechem son his all [those who] went out of [the] gate of city his and they were circumcised every male all [those who] went out of [the] gate of city his.
Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 And it was on the day third when were they in pain and they took two of [the] sons of Jacob Simeon and Levi [the] brothers of Dinah each sword his and they went on the city security and they killed every male.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 And Hamor and Shechem son his they slew to [the] mouth of [the] sword and they took Dinah from [the] house of Shechem and they went out.
Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 [the] sons of Jacob they came on the [ones] slain and they plundered the city that people had defiled sister their.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
28 Flock[s] their and herd[s] their and donkeys their and [that] which [was] in the city and [that] which [was] in the field they took.
Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
29 And all wealth their and all little one[s] their and wives their they took captive and they plundered and all that [was] in the house.
Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
30 And he said Jacob to Simeon and to Levi you have troubled me by making odious me among [the] inhabitant[s] of the land among the Canaanite[s] and among the Perizzite[s] and I [am] men of number and they will gather on me and they will attack me and I will be destroyed I and household my.
Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
31 And they said ¿ like a prostitute will he use sister our.
Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”

< Genesis 34 >