< Ezekiel 9 >
1 And he called out in ears my a voice great saying they have drawn near [the] punishments of the city and everyone [the] weapon of destruction his [is] in hand his.
Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
2 And there! six men [were] coming - from [the] direction of [the] gate upper which - [is] faced north-ward and everyone [the] weapon of shattering his [was] in hand his and a man one [was] in midst of them clothed linen and [the] writing-case of scribe [was] at hips his and they came and they stood beside [the] altar of bronze.
Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
3 And [the] glory of - [the] God of Israel it was taken up from on the cherub which it had been on it to [the] threshold of the house and he called to the man who was clothed the linen whom writing-case of scribe [was] at hips his.
Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
4 And he said Yahweh (to him *Q(k)*) pass in [the] midst of the city in [the] midst of Jerusalem and you will mark a mark on [the] foreheads of the people who sigh and who groan on all the abominations which are done in [the] midst of it.
Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
5 And to these he said in ears my pass in the city after him and strike (not *Q(K)*) let it look with compassion (eye your *Q(K)*) and may not you show pity.
Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
6 Old [man] young man and virgin and little one[s] and women you will kill to destruction and to any person whom [is] on him the mark may not you draw near and from sanctuary my you will begin and they began with the men old who [were] before the house.
Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
7 And he said to them make unclean the house and fill the courts [those] slain go forth and they went forth and they struck in the city.
Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
8 And it was when were striking they and [was] remaining I and I fell! on face my and I cried out and I said alas! O Lord Yahweh ¿ about to destroy [are] you all [the] remnant of Israel when pouring out you rage your on Jerusalem.
Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
9 And he said to me [the] iniquity of [the] house of Israel and Judah [is] great with muchness muchness and it has been filled the land blood and the city it is full perverseness for they have said he has forsaken Yahweh the land and not Yahweh [is] seeing.
Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
10 And also I not it will look with compassion eye my and not I will show pity conduct their on own head their I will requite.
Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
11 And there! the man - clothed of the linen whom the writing-case [was] at hips his [was] bringing back a word saying I have done (according to all that *Q(K)*) you commanded me.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”