< Ezekiel 18 >
1 And it came [the] word of Yahweh to me saying.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 What? [is] to you you [are] speaking a proverb the proverb this on [the] land of Israel saying parents they eat sour grape[s] and [the] teeth of the children (they are blunt. *LA(bh)*)
“Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
3 [by] [the] life Of me [the] utterance of [the] Lord Yahweh if it will belong to you again to speak a proverb the proverb this in Israel.
“Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
4 Here! all lives [belong] to me they as [the] life of the parent and as [the] life of the child [belong] to me they the soul which sins it it will die.
Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
5 And anyone for he will be righteous and he will do justice and righteousness.
“Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
6 To the mountains not he has eaten and eyes his not he has lifted up to [the] idols of [the] house of Israel and [the] wife of neighbor his not he has defiled and to a woman menstruation not he drew near.
tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
7 And anyone not he oppressed pledge his a debt he returned robbery not he robbed food his to [the] hungry he gave and [the] naked he covered clothing.
Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
8 For interest not he lent and interest not he took from injustice he turned away hand his justice of faithfulness he did between a person and a person.
Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
9 In statutes my he walked and judgments my he has kept by doing faithfulness [is] righteous he certainly he will live [the] utterance of [the] Lord Yahweh.
Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
10 And he will father a son violent [who] sheds blood and he will do alas! any one of these [things].
“Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
11 And he all these [things] not he did for also to the mountains he has eaten and [the] wife of neighbor his he has defiled.
(tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
12 [the] poor And [the] needy he has oppressed robberies he has robbed a pledge not he returned and to the idols he has lifted up eyes his abomination he has done.
Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
13 For interest he has lent and interest he has taken and will he live? not he will live all the abominations these he has done certainly he will be put to death blood his on him it will be.
Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
14 And there! he has fathered a child and he has seen all [the] sins of father his which he did and he saw and not he did like them.
“Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
15 On the mountains not he has eaten and eyes his not he has lifted up to [the] idols of [the] house of Israel [the] wife of neighbor his not he has defiled.
“Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
16 And anyone not he has oppressed a pledge not he has taken as pledge and robbery not he has robbed food his to [the] hungry he has given and [the] naked he has covered clothing.
tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
17 From [the] poor he has turned away hand his interest and interest not he has taken judgments my he has done in statutes my he has walked he not he will die for [the] iniquity of father his certainly he will live.
Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
18 Father his for he has extorted extortion he has robbed robbery of a brother and [that] which not [was] good he has done in among people his and there! he will die for iniquity his.
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
19 And you say why? not has he borne the child in [the] iniquity of the parent and the child justice and righteousness he has done all statutes my he has kept and he has done them certainly he will live.
“Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
20 The soul which sins it it will die a child not he will bear - in [the] iniquity of the parent and a parent not he will bear in [the] iniquity of the child [the] righteousness of the righteous [person] on him it will be and [the] wickedness of (the wicked [person] *Q(K)*) on him it will be.
Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
21 And the wicked [person] if he will turn away from all (sins his *Q(K)*) which he has done and he will keep all (statutes my *LAB(h)*) and he will do justice and righteousness certainly he will live not he will die.
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
22 All transgressions his which he has done not they will be remembered to him for righteousness his which he has done he will live.
A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
23 ¿ Really do I take pleasure in [the] death of [the] wicked [the] utterance of [the] Lord Yahweh ¿ not when turning back he from ways his and he will live.
Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
24 And when turns away [the] righteous from righteousness his and he will do injustice according to all the abominations which he did the wicked [person] he will do and will he live? all (righteousness his *Q(K)*) which he did not they will be remembered for unfaithfulness his which he has acted unfaithfully and for sin his which he has sinned for them he will die.
“Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
25 And you say not it is correct [the] way of [the] Lord listen please O house of Israel ¿ way my not is it correct ¿ not ways your not are they correct.
“Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
26 When turns away [the] righteous from righteousness his and he will do injustice and he will die on them for injustice his which he has done he will die.
Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
27 And when turns away [the] wicked from wickedness his which he has done and he did justice and righteousness he life his he will preserve alive.
Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
28 And he saw (and he turned away *Q(k)*) from all transgressions his which he had done certainly he will live not he will die.
Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
29 And they say [the] house of Israel not it is correct [the] way of [the] Lord ¿ ways my not are they correct O house of Israel ¿ not ways your not is it correct.
Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
30 Therefore everyone according to ways his I will judge you O house of Israel [the] utterance of [the] Lord Yahweh turn back and turn away from all transgressions your and not it will become for you a stumbling block iniquity.
“Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
31 Throw away from with you all transgressions your which you have transgressed by them and make for yourselves a heart new and a spirit new and why? will you die O house of Israel.
Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
32 For not I take pleasure in [the] death of the [one who] dies [the] utterance of [the] Lord Yahweh and turn away and live.
Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!