< Amos 1 >
1 [the] words of Amos who he was among the sheep-tenders from Tekoa which he saw on Israel in [the] days of - (Uzziah *L(abh)*) [the] king of Judah and in [the] days of Jeroboam [the] son of Joash [the] king of Israel two years before the earthquake.
Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 And he said - Yahweh (from Zion *L(abh)*) he will roar and from Jerusalem he will give forth voice his and they will dry up [the] pastures of the shepherds and it will wither [the] top of Carmel.
Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
3 Thus he says Yahweh on three transgressions of Damascus and on four not I will revoke it because threshed they with [the] threshing sledges of iron Gilead.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
4 And I will send forth a fire on [the] house of Hazael and it will consume [the] fortresses of Ben Hadad.
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 And I will break [the] bar of Damascus and I will cut off inhabitant[s] from [the] Valley of Aven and a holder of a scepter from Beth Eden and they will go into exile [the] people of Aram Kir towards he says Yahweh.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
6 Thus he says Yahweh on three transgressions of Gaza and on four not I will revoke it because carried away into exile they exile complete to deliver up [them] to Edom.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 And I will send forth a fire on [the] wall of Gaza and it will consume fortresses its.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
8 And I will cut off inhabitant[s] from Ashdod and a holder of a scepter from Ashkelon and I will turn hand my on Ekron and they will perish [the] remnant of [the] Philistines he says [the] Lord Yahweh.
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Thus he says Yahweh on three transgressions of Tyre and on four not I will revoke it because delivered up they exile complete to Edom and not they remembered [the] covenant of brothers.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
10 And I will send forth a fire on [the] wall of Tyre and it will consume fortresses its.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 Thus he says Yahweh on three transgressions of Edom and on four not I will revoke it because pursued he with the sword brother his and he spoiled compassion his and it tore for ever anger his and fury his he kept it perpetuity.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
12 And I will send forth a fire on Teman and it will consume [the] fortresses of Bozrah.
Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 Thus he says Yahweh on three transgressions of [the] people of Ammon and on four not I will revoke it because ripped open they [the] pregnant [women] of Gilead so as to enlarge territory their.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 And I will kindle a fire on [the] wall of Rabbah and it will consume fortresses its with a shout of alarm on [the] day of battle with a storm on [the] day of (a storm-wind *L(abh)*)
Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 and he will go king their in exile he and officials his together he says Yahweh.
Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.