< 1 Samuel 22 >

1 And he went David from there and he escaped to [the] cave of Adullam and they heard brothers his and all [the] household of father his and they went down to him there towards.
Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
2 And they gathered together to him every man of distress and every man whom [belonged] to him a creditor and every man bitter of soul and he became over them a commander and they were with him about four hundred man.
Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
3 And he went David from there Mizpah of Moab and he said - to [the] king of Moab let him go out please father my and mother my with you until that I will know what? will he do for me God.
Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
4 And he led them with [the] presence of [the] king of Moab and they remained with him all [the] days of [the] being of David in the stronghold.
Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
5 And he said Gad the prophet to David not you must remain in the stronghold go and you will go for yourself [the] land of Judah and he went David and he came [the] forest of Hereth.
Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
6 And he heard Saul that he was known David and [the] men who [were] with him and Saul [was] sitting at Gibeah under the tamarisk tree at the high place and spear his [was] in hand his and all servants his [were] standing with him.
Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
7 And he said Saul to servants his who were standing with him listen please O Ben-jaminites also? to all of you will he give [the] son of Jesse fields and vineyards all of you will he appoint commanders of thousands and commanders of hundreds.
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
8 For you have conspired all of you on me and there not [is one who] opens ear my when made son my with [the] son of Jesse and not [was] feeling pain any of you on me and opening ear my that he has raised up son my servant my on me to an ambusher as the day this.
Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
9 And he answered Doeg the Edomite and he [was] standing with [the] servants of Saul and he said I saw [the] son of Jesse coming Nob towards to Ahimelech [the] son of Ahitub.
Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
10 And he enquired for him by Yahweh and food he gave to him and [the] sword of Goliath the Philistine he gave to him.
Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
11 And he sent the king to summon Ahimelech [the] son of Ahitub the priest and all [the] house of father his the priests who [were] at Nob and they came all of them to the king.
Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
12 And he said Saul listen please O son of Ahitub and he said here [am] I O lord my.
Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
13 And he said (to him *Q(k)*) Saul why? have you conspired on me you and [the] son of Jesse when giving you to him bread and a sword and [you] enquired for him by God to rise up against me to an ambusher as the day this.
Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
14 And he answered Ahimelech the king and he said and who? among all servants your [is] like David faithful and [the] son-in-law of the king and [one who] turns aside to bodyguard your and honored in household your.
Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
15 This day did I begin? (to enquire *Q(k)*) for him by God far be it to me may not he put the king against servant his anything against all [the] house of father my for not he knew servant your in all this anything small or great.
Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
16 And he said the king certainly you will die O Ahimelech you and all [the] house of father your.
Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
17 And he said the king to the runners who were standing with him turn round and put to death - [the] priests of Yahweh for also hand their [is] with David and for they knew that [was] fleeing he and not they uncovered (ear my *Q(K)*) and not they were willing [the] servants of the king to stretch out hand their to fall on [the] priests of Yahweh.
Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
18 And he said the king (to Doeg *Q(k)*) turn round you and fall on the priests and he turned round (Doeg *Q(k)*) the Edomite and he fell he on the priests and he killed - on the day that eighty and five man [who] carried an ephod of linen.
Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
19 And Nob [the] city of the priests he struck to [the] mouth of [the] sword from man and unto woman from child and unto suckling-child and ox[en] and donkey[s] and sheep to [the] mouth of [the] sword.
Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
20 And he escaped a son one of Ahimelech [the] son of Ahitub and name his [was] Abiathar and he fled after David.
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
21 And he told Abiathar to David that he had killed Saul [the] priests of Yahweh.
Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
22 And he said David to Abiathar I knew on the day that that [was] there (Doeg *Q(k)*) the Edomite that certainly he will tell to Saul I I have turned in every life of [the] house of father your.
Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
23 Remain! with me may not you be afraid for [the one] who he seeks life my he seeks life your for [are] in good care you with me.
Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”

< 1 Samuel 22 >