< 1 Chronicles 5 >

1 And [the] sons of Reuben [the] firstborn of Israel for he [was] the firstborn and when profaned he [the] beds of father his it was given birthright his to [the] sons of Joseph [the] son of Israel and not to have themselves enrolled to the birthright.
Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
2 For Judah he was strong among brothers his and to a leader [was] from him and the birthright [belonged] to Joseph.
Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
3 [the] sons of Reuben [the] firstborn of Israel Hanoch and Pallu Hezron and Carmi.
àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
4 [the] descendants of Joel Shemaiah son his Gog son his Shimei son his.
Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
5 Micah son his Reaiah son his Baal son his.
Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
6 Beerah son his whom he took into exile Tiglath-pileser [the] king of Assyria he [was] a leader of the Reubenite[s].
Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
7 And relatives his to clans his by genealogical enrolment to generations their [were] the chief Jeiel and Zechariah.
Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
8 And Bela [the] son of Azaz [the] son of Shema [the] son of Joel he [was] dwelling in Aroer and to Nebo and Baal Meon.
àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
9 And to the east he dwelt till to [the] entrance of [the] wilderness from the river Euphrates for livestock their they had increased in [the] land of Gilead.
Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
10 And in [the] days of Saul they made war with the Hagrites and they fell by hand their and they dwelt in tents their on all [the] face of [the] east of Gilead.
Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
11 And [the] descendants of Gad to before them they dwelt in [the] land of Bashan to Salecah.
Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
12 Joel [was] the chief and Shapham [was] the second and Janai and Shaphat in Bashan.
Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
13 And relatives their to [the] house of ancestors their Michael and Meshullam and Sheba and Jorai and Jakan and Zia and Eber seven.
Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
14 These - [were] [the] sons of Abihail [the] son of Huri [the] son of Jaroah [the] son of Gilead [the] son of Michael [the] son of Jeshishai [the] son of Jahdo [the] son of Buz.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
15 Ahi [the] son of Abdiel [the] son of Guni [was] chief of [the] house of ancestors their.
Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 And they dwelt in Gilead in Bashan and in daughters its and in all [the] pasture lands of Sharon on (extremities their. *LA(bh)*)
Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
17 All of them they had themselves enrolled in [the] days of Jotham [the] king of Judah and in [the] days Jeroboam [the] king of Israel.
Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
18 [the] descendants of Reuben and [the] Gadite[s] and [the] half of [the] tribe of Manasseh from [the] sons of strength men [who] carried shield and sword and [who] bent a bow and [who] were trained of warfare forty and four thousand and seven hundred and sixty [those who] went forth of war.
Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
19 And they made war with the Hagrites and Jetur and Naphish and Nodab.
Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
20 And they were helped on them and they were given in hand their the Hagrites and all [those] who [were] with them for to God they had cried out in the battle and he was entreated by them for they trusted in him.
Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
21 And they took captive livestock their camels their fifty thousand and sheep two hundred and fifty thousand and donkeys two thousand and person[s] of humankind one hundred thousand.
Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
22 For slain [ones] many they fell for [was] from God the battle and they dwelt in place of them until the exile.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
23 And [the] descendants of [the] half of [the] tribe of Manasseh they dwelt in the land from Bashan to Baal Hermon and Senir and [the] mountain of Hermon they they multiplied.
Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
24 And these [were] [the] chiefs of [the] house of ancestors their and Epher and Ishi and Eliel and Azriel and Jeremiah and Hodaviah and Jahdiel men mighty of strength men of names chiefs of [the] house of ancestors their.
Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
25 And they acted unfaithfully against [the] God of ancestors their and they played [the] prostitute after [the] gods of [the] peoples of the land which he had destroyed God from before them.
Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
26 And he stirred up [the] God of Israel [the] spirit of - Pul [the] king of Assyria and [the] spirit of Tiglath-pileser [the] king of Assyria and he took into exile them to the Reubenite[s] and to the Gadite[s] and to [the] half of [the] tribe of Manasseh and he brought them to Halah and Habor and Hara and [the] river of Gozan until the day this.
Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

< 1 Chronicles 5 >